ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àìsáyà 25:8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  8 Ó máa gbé ikú mì* títí láé,+

      Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ sì máa nu omijé kúrò ní ojú gbogbo èèyàn.+

      Ó máa mú ẹ̀gàn àwọn èèyàn rẹ̀ kúrò ní gbogbo ayé,

      Torí Jèhófà fúnra rẹ̀ ti sọ ọ́.

  • Hósíà 13:14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 14 Màá rà wọ́n pa dà lọ́wọ́ agbára Isà Òkú;*

      Màá gbà wọ́n pa dà lọ́wọ́ ikú.+

      Ìwọ Ikú, oró rẹ dà?+

      Ìwọ Isà Òkú, ìpanirun rẹ dà?+

      Síbẹ̀, mi ò ní fojú àánú wò wọ́n.*

  • Máàkù 12:26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 26 Àmọ́ ní ti àjíǹde àwọn òkú, ṣé ẹ ò tíì kà á nínú ìwé Mósè ni, nínú ìtàn igi ẹlẹ́gùn-ún, pé Ọlọ́run sọ fún un pé: ‘Èmi ni Ọlọ́run Ábúráhámù, Ọlọ́run Ísákì àti Ọlọ́run Jékọ́bù’?+

  • Jòhánù 5:28, 29
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 28 Ẹ má ṣe jẹ́ kí èyí yà yín lẹ́nu, torí wákàtí náà ń bọ̀, tí gbogbo àwọn tó wà nínú ibojì ìrántí máa gbọ́ ohùn rẹ̀,+ 29 tí wọ́n á sì jáde wá, àwọn tó ṣe ohun rere sí àjíǹde ìyè, àwọn tó sọ ohun burúkú dàṣà sí àjíǹde ìdájọ́.+

  • Jòhánù 11:24, 25
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Màtá sọ fún un pé: “Mo mọ̀ pé ó máa dìde nígbà àjíǹde+ ní ọjọ́ ìkẹyìn.” 25 Jésù sọ fún un pé: “Èmi ni àjíǹde àti ìyè.+ Ẹni tó bá ní ìgbàgbọ́ nínú mi, tó bá tiẹ̀ kú, ó máa yè;

  • Ìṣe 24:15
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Mo ní ìrètí nínú Ọlọ́run, ìrètí tí àwọn ọkùnrin yìí náà ní, pé àjíǹde+ àwọn olódodo àti àwọn aláìṣòdodo+ yóò wà.

  • 1 Kọ́ríńtì 15:21
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 Nítorí bí ikú ṣe wá nípasẹ̀ ẹnì kan,+ àjíǹde òkú náà wá nípasẹ̀ ẹnì kan.+

  • 1 Tẹsalóníkà 4:14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 14 Nítorí tí a bá nígbàgbọ́ pé Jésù kú, ó sì jí dìde,+ lọ́nà kan náà, Ọlọ́run yóò mú àwọn tó ti sùn nínú ikú nítorí Jésù wá sí ìyè pẹ̀lú rẹ̀.+

  • Ìfihàn 20:12, 13
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 Mo rí àwọn òkú, ẹni ńlá àti ẹni kékeré, wọ́n dúró síwájú ìtẹ́ náà, a sì ṣí àwọn àkájọ ìwé sílẹ̀. Àmọ́ a ṣí àkájọ ìwé míì; àkájọ ìwé ìyè ni.+ A fi àwọn ohun tí a kọ sínú àkájọ ìwé náà ṣèdájọ́ àwọn òkú bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn ṣe rí.+ 13 Òkun yọ̀ǹda àwọn òkú tó wà nínú rẹ̀, ikú àti Isà Òkú* yọ̀ǹda àwọn òkú tó wà nínú wọn, a sì ṣèdájọ́ ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn ṣe rí.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́