-
Jeremáyà 21:7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 “‘Jèhófà sọ pé, “Lẹ́yìn náà, màá fi Sedekáyà ọba Júdà àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn èèyàn ìlú yìí, ìyẹn àwọn tó bọ́ lọ́wọ́ àjàkálẹ̀ àrùn, idà àti ìyàn, lé ọwọ́ Nebukadinésárì* ọba Bábílónì, lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn àti lé ọwọ́ àwọn tó fẹ́ gba ẹ̀mí wọn.*+ Á fi idà pa wọ́n. Kò ní bá wọn kẹ́dùn, bẹ́ẹ̀ ni kò ní yọ́nú sí wọn tàbí kó ṣàánú wọn.”’+
-
-
Jeremáyà 34:18-20Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
18 Ohun tó sì máa ṣẹlẹ̀ nìyí sí àwọn tó da májẹ̀mú mi, tí wọn kò mú ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí wọ́n dá lójú mi ṣẹ, nígbà tí wọ́n gé ọmọ màlúù sí méjì, tí wọ́n sì gba àárín rẹ̀ kọjá,+ 19 ìyẹn, àwọn ìjòyè Júdà àti àwọn ìjòyè Jerúsálẹ́mù, àwọn òṣìṣẹ́ ààfin àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú gbogbo èèyàn ilẹ̀ náà tí wọ́n kọjá láàárín ọmọ màlúù tí wọ́n gé sí méjì náà: 20 Ṣe ni màá fà wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn àti àwọn tó fẹ́ gba ẹ̀mí wọn,* òkú wọn á sì di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹran orí ilẹ̀.+
-