15 Mo wà pẹ̀lú rẹ, màá dáàbò bò ọ́ ní gbogbo ibi tí o bá lọ, màá sì mú ọ pa dà sí ilẹ̀ yìí.+ Mi ò ní fi ọ́ sílẹ̀ títí màá fi ṣe ohun tí mo ṣèlérí fún ọ.”+
12 Ó fèsì pé: “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ,+ ohun tí yóò sì jẹ́ àmì fún ọ pé èmi ni mo rán ọ nìyí: Lẹ́yìn tí o bá ti mú àwọn èèyàn náà kúrò ní Íjíbítì, ẹ máa jọ́sìn* Ọlọ́run tòótọ́ lórí òkè yìí.”+
5 Kò sẹ́ni tó máa lè dìde sí ọ ní gbogbo ìgbà tí o bá fi wà láàyè.+ Bí mo ṣe wà pẹ̀lú Mósè ni màá ṣe wà pẹ̀lú rẹ.+ Mi ò ní pa ọ́ tì, mi ò sì ní fi ọ́ sílẹ̀.+