24 Jèhófà wá rọ òjò imí ọjọ́ àti iná lé Sódómù àti Gòmórà lórí, ó wá látọ̀dọ̀ Jèhófà, láti ọ̀run.+25 Ó run àwọn ìlú yìí, àní, gbogbo agbègbè náà, títí kan àwọn tó ń gbé àwọn ìlú náà àti àwọn ewéko ilẹ̀.+
12 Ó ti ṣe ohun tó sọ lòdì sí àwa+ àti àwọn alákòóso wa tí wọ́n jọba lé wa lórí,* torí ó mú kí àjálù ńlá ṣẹlẹ̀ sí wa; ohunkóhun ò ṣẹlẹ̀ rí lábẹ́ gbogbo ọ̀run bí èyí tó ṣẹlẹ̀ ní Jerúsálẹ́mù.+