Jeremáyà 5:31 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́,+Àwọn àlùfáà sì ń fi àṣẹ wọn tẹ àwọn èèyàn lórí ba. Àwọn èèyàn mi sì fẹ́ ẹ bẹ́ẹ̀.+ Àmọ́, kí lẹ máa ṣe nígbà tí òpin bá dé?” Jeremáyà 14:14 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 14 Jèhófà wá sọ fún mi pé: “Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni àwọn wòlíì náà ń sọ ní orúkọ mi.+ Mi ò rán wọn, bẹ́ẹ̀ ni mi ò pàṣẹ fún wọn, mi ò sì bá wọn sọ̀rọ̀.+ Ìran èké àti ìwoṣẹ́ asán àti ẹ̀tàn ọkàn wọn ni wọ́n ń sọ tẹ́lẹ̀ fún yín.+ Míkà 3:11 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 11 Àwọn olórí* rẹ̀ ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kí wọ́n tó dájọ́,+Àwọn àlùfáà rẹ̀ ń gba owó kí wọ́n tó kọ́ni,+Àwọn wòlíì rẹ̀ ń gba owó* kí wọ́n tó woṣẹ́.+ Síbẹ̀ wọ́n gbára lé Jèhófà,* wọ́n ń sọ pé: “Ṣebí Jèhófà wà pẹ̀lú wa?+ Àjálù kankan ò lè dé bá wa.”+ Sefanáyà 3:4 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 4 Aláfojúdi ni àwọn wòlíì rẹ̀, oníbékebèke ni wọ́n.+ Àwọn àlùfáà rẹ̀ ń sọ ohun mímọ́ di ẹlẹ́gbin;+Wọ́n ń rú òfin.+
31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́,+Àwọn àlùfáà sì ń fi àṣẹ wọn tẹ àwọn èèyàn lórí ba. Àwọn èèyàn mi sì fẹ́ ẹ bẹ́ẹ̀.+ Àmọ́, kí lẹ máa ṣe nígbà tí òpin bá dé?”
14 Jèhófà wá sọ fún mi pé: “Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni àwọn wòlíì náà ń sọ ní orúkọ mi.+ Mi ò rán wọn, bẹ́ẹ̀ ni mi ò pàṣẹ fún wọn, mi ò sì bá wọn sọ̀rọ̀.+ Ìran èké àti ìwoṣẹ́ asán àti ẹ̀tàn ọkàn wọn ni wọ́n ń sọ tẹ́lẹ̀ fún yín.+
11 Àwọn olórí* rẹ̀ ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kí wọ́n tó dájọ́,+Àwọn àlùfáà rẹ̀ ń gba owó kí wọ́n tó kọ́ni,+Àwọn wòlíì rẹ̀ ń gba owó* kí wọ́n tó woṣẹ́.+ Síbẹ̀ wọ́n gbára lé Jèhófà,* wọ́n ń sọ pé: “Ṣebí Jèhófà wà pẹ̀lú wa?+ Àjálù kankan ò lè dé bá wa.”+
4 Aláfojúdi ni àwọn wòlíì rẹ̀, oníbékebèke ni wọ́n.+ Àwọn àlùfáà rẹ̀ ń sọ ohun mímọ́ di ẹlẹ́gbin;+Wọ́n ń rú òfin.+