-
Dáníẹ́lì 4:23-26Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
23 “‘Ọba wá rí olùṣọ́ kan, ẹni mímọ́,+ tó ń sọ̀ kalẹ̀ láti ọ̀run, ó ń sọ pé: “Ẹ gé igi náà lulẹ̀, kí ẹ sì pa á run, àmọ́ ẹ fi kùkùté igi náà sílẹ̀ pẹ̀lú gbòǹgbò rẹ̀* nínú ilẹ̀, kí ẹ sì fi ọ̀já irin àti bàbà dè é láàárín koríko pápá. Ẹ jẹ́ kí ìrì ọ̀run sẹ̀ sí i, kí ìpín rẹ̀ sì wà pẹ̀lú àwọn ẹranko títí ìgbà méje fi máa kọjá lórí rẹ̀.”+ 24 Ìtumọ̀ rẹ̀ nìyí, ọba; àṣẹ tí Ẹni Gíga Jù Lọ pa, tó gbọ́dọ̀ ṣẹlẹ̀ sí olúwa mi ọba ni. 25 Wọ́n máa lé ọ kúrò láàárín àwọn èèyàn, ọ̀dọ̀ àwọn ẹranko ni wàá máa gbé, a sì máa fún ọ ní ewéko jẹ bí akọ màlúù; ìrì ọ̀run máa sẹ̀ sí ọ lára,+ ìgbà méje + sì máa kọjá lórí rẹ,+ títí o fi máa mọ̀ pé Ẹni Gíga Jù Lọ ni Alákòóso nínú ìjọba aráyé, ẹni tó bá sì wù ú ló ń gbé e fún.+
26 “‘Àmọ́ torí wọ́n sọ pé kí wọ́n fi kùkùté igi náà sílẹ̀ pẹ̀lú gbòǹgbò rẹ̀,*+ ìjọba rẹ máa pa dà di tìrẹ lẹ́yìn tí o bá mọ̀ pé ọ̀run ló ń ṣàkóso.
-