-
1 Sámúẹ́lì 2:7, 8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 Ó ń gbé aláìní dìde látinú eruku;
Ti Jèhófà ni àwọn ìpìlẹ̀ ayé,+
Ó sì gbé ilẹ̀ tó ń mú èso jáde ka orí wọn.
-
-
Jóòbù 34:24Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
24 Ó ń fọ́ àwọn alágbára túútúú láì ṣẹ̀ṣẹ̀ máa ṣèwádìí,
Ó sì ń fi àwọn míì rọ́pò wọn.+
-
-
Dáníẹ́lì 7:13, 14Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
13 “Mò ń wò nínú ìran òru, sì wò ó! ẹnì kan bí ọmọ èèyàn+ ń bọ̀ pẹ̀lú ìkùukùu* ojú ọ̀run; a jẹ́ kó wọlé wá sọ́dọ̀ Ẹni Ọjọ́ Àtayébáyé,+ wọ́n sì mú un wá sún mọ́ iwájú Ẹni yẹn. 14 A sì fún un ní àkóso,+ ọlá+ àti ìjọba, pé kí gbogbo àwọn èèyàn, orílẹ̀-èdè àti ẹ̀yà máa sìn ín.+ Àkóso rẹ̀ jẹ́ àkóso tó máa wà títí láé, tí kò ní kọjá lọ, ìjọba rẹ̀ ò sì ní pa run.+
-