-
Jeremáyà 49:14-16Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
14 Mo ti gbọ́ ìròyìn kan látọ̀dọ̀ Jèhófà,
Aṣojú kan ti lọ jíṣẹ́ fún àwọn orílẹ̀-èdè pé:
“Ẹ kóra jọ, ẹ wá gbéjà kò ó;
Ẹ sì múra ogun.”+
15 “Nítorí, wò ó! Mo ti sọ ọ́ di ẹni tí kò já mọ́ nǹkan kan láàárín àwọn orílẹ̀-èdè,
O ti tẹ́ láàárín àwọn èèyàn.+
16 Bí o ṣe ń kó jìnnìjìnnì bá àwọn èèyàn
Àti ìgbéraga* ọkàn rẹ ti tàn ọ́ jẹ,
Ìwọ tó ń gbé ihò inú àpáta,
Tí ò ń gbé ní òkè tó ga jù lọ.
Bí o bá tiẹ̀ kọ́ ìtẹ́ rẹ sí ibi gíga bí ẹyẹ idì,
Màá rẹ̀ ọ́ wálẹ̀ láti ibẹ̀,” ni Jèhófà wí.
-