ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • scl ojú ìwé 106-107
  • Òdodo

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Òdodo
  • Àwọn Ẹsẹ Bíbélì Tó Lè Ran Àwa Kristẹni Lọ́wọ́
Àwọn Ẹsẹ Bíbélì Tó Lè Ran Àwa Kristẹni Lọ́wọ́
scl ojú ìwé 106-107

Òdodo

Ta lẹni kan ṣoṣo tó lẹ́tọ̀ọ́ láti pinnu ohun tó tọ́ àti ohun tí kò tọ́?

Di 32:4; Isk 33:17-20

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Jẹ 18:23-33—Jèhófà jẹ́ kí Ábúráhámù mọ̀ pé Onídàájọ́ òdodo lòun

    • Sm 72:1-4, 12-14—Ọlọ́run mí sí onísáàmù yìí láti yin Mèsáyà Ọba, ẹni tó jẹ́ olódodo bíi ti Ọlọ́run

Tá a bá ń tẹ̀ lé àwọn ìlànà òdodo Jèhófà, àǹfààní wo la máa rí?

Sm 37:25, 29; Jem 5:16; 1Pe 3:12

Tún wo Sm 35:24; Ais 26:9; Ro 1:17

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Job 37:22-24—Élíhù yin Jèhófà torí pé ó jẹ́ olódodo, títóbi rẹ̀ sì máa ń mú káwọn èèyàn rẹ̀ bọ̀wọ̀ fún un látọkàn wá

    • Sm 89:13-17—Onísáàmù yìí yin Jèhófà torí pé òdodo ló fi ń ṣàkóso

Kí ló túmọ̀ sí pé kéèyàn wá òdodo Ọlọ́run?

Isk 18:25-31; Mt 6:33; Ro 12:1, 2; Ef 4:23, 24

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Jẹ 6:9, 22; 7:1—Nóà ṣe gbogbo ohun tí Jèhófà ní kó ṣe, ìyẹn sì fi hàn pé ó jẹ́ olódodo

    • Ro 4:1-3, 9—Ábúráhámù nígbàgbọ́ tó lágbára nínú Jèhófà, torí náà Jèhófà kà á sí olódodo

Kí nìdí tó fi jẹ́ pé ìfẹ́ tá a ní fún Jèhófà ló yẹ kó mú ká máa hùwà tó dáa, kì í ṣe torí pé a fẹ́ gbayì lójú àwọn èèyàn?

Mt 6:1; 23:27, 28; Lk 16:14, 15; Ro 10:10

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Mt 5:20; 15:7-9—Jésù sọ fáwọn èèyàn pé kí wọ́n jẹ́ olódodo, àmọ́ kì í ṣe bíi tàwọn akọ̀wé òfin àtàwọn Farisí torí pé alágàbàgebè ni wọ́n

    • Lk 18:9-14—Jésù sọ àpèjúwe kan tó jẹ́ káwọn tó máa ń ṣe òdodo àṣelékè, tí wọ́n sì máa ń wo àwọn míì bíi pé wọn ò já mọ́ nǹkan kan rí i pé ó yẹ kí wọ́n ṣàtúnṣe

Kí nìdí tó fi dáa kéèyàn níwà rere ju kó jẹ́ olódodo?

Ro 5:7, 8

Tún wo Lk 6:33-36; Iṣe 14:16, 17; Ro 12:20, 21; 1Tẹ 5:15

Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa ṣe òdodo àṣelékè tàbí ká máa ṣe bíi pé òdodo wa ju tàwọn míì lọ?

Onw 7:16; Ais 65:5; Ro 10:3; 14:10

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́