ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • scl ojú ìwé 16-18
  • Àṣà Burúkú

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àṣà Burúkú
  • Àwọn Ẹsẹ Bíbélì Tó Lè Ran Àwa Kristẹni Lọ́wọ́
Àwọn Ẹsẹ Bíbélì Tó Lè Ran Àwa Kristẹni Lọ́wọ́
scl ojú ìwé 16-18

Àṣà Burúkú

Àwọn àṣà burúkú wo ló yẹ káwa Kristẹni máa yẹra fún?

Àbẹ̀tẹ́lẹ̀

Ẹk 23:8; Sm 26:9, 10; Owe 17:23

Tún wo Di 10:17; 16:19; Sm 15:1, 5

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 1Sa 8:1-5—Dípò káwọn ọmọ wòlíì Sámúẹ́lì tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rere bàbá wọn, ńṣe ni wọ́n ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tí wọ́n sì ń yí ìdájọ́ po

    • Ne 6:10-13—Àwọn ọ̀tá gba Ṣemáyà pé kó lọ sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké kó lè dẹ́rù ba Gómìnà Nehemáyà, kí iṣẹ́ Jèhófà lè dúró

Àjẹkì

Owe 23:20, 21; 28:7

Tún wo Lk 21:34, 35

Àríyá aláriwo

Ro 13:13; Ga 5:19, 21; 1Pe 4:3

Tún wo Owe 20:1; 1Kọ 10:31

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Da 5:1-4, 30—Nígbà tí Ọba Bẹliṣásárì se “àsè ńlá” ó mutí yó, ó sì tàbùkù sí Jèhófà. Ohun tó ṣe yẹn ló yọrí sí ikú ẹ̀

Àwòrán Ìṣekúṣe

Wo “Àwòrán Ìṣekúṣe”

Fífi ọ̀rọ̀ dídùn pọ́nni

Job 32:21, 22; Sm 5:9; 12:2, 3; Owe 26:24-28; 29:5

Tún wo Owe 28:23; 1Tẹ 2:3-6

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Lk 18:18, 19—Jésù ò fẹ́ kí wọ́n fi ọ̀rọ̀ dídùn pọ́n òun

    • Iṣe 12:21-23—Ọba Hẹ́rọ́dù Ágírípà kú torí pé ó gbà kí wọ́n pé òun ní ọlọ́run

Fífọ́nnu

Wo “Fífọ́nnu”

Ìbánidíje

Onw 4:4; Ga 5:26

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Mk 9:33-37; 10:35-45—Léraléra ni Jésù bá àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ wí torí pé wọ́n máa ń bára wọn jiyàn lórí ẹni tó jẹ́ ọ̀gá láàárín wọn

    • 3Jo 9, 10—Díótíréfè fẹ́ “fi ara rẹ̀ ṣe olórí láàárín” àwọn ará

Ìbọ̀rìṣà

Wo “Ìbọ̀rìṣà”

Ìfiniṣẹ̀sín

Owe 19:29; 24:9

Tún wo Owe 17:5; 22:10; 2Pe 3:3, 4

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 2Kr 36:15-21—Ọlọ́run fìyà jẹ àwọn èèyàn ẹ̀ tó jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ torí pé wọ́n ń fi àwọn òjíṣẹ́ rẹ̀ ṣẹ̀sín, wọ́n sì ń fi àwọn wòlíì rẹ̀ ṣe yẹ̀yẹ́

    • Job 12:4; 17:2; 21:3; 34:7—Àwọn èèyàn ń fi Jóòbù ṣe yẹ̀yẹ́ nígbà tó ń dojú kọ àdánwò tó le gan-an

Ìjà

Wo “Ìjà”

Ìlọ́nilọ́wọ́gbà

Sm 62:10; 1Kọ 5:10, 11; 6:9, 10

Tún wo Owe 1:19; 15:27

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Jer 22:11-17—Jèhófà fìyà jẹ Ọba Ṣálúmù (Jèhóáhásì) torí pé ó jẹ́ alọ́nilọ́wọ́gbà, ó sì tún dá àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tó burú gan-an

    • Lk 19:2, 8—Sákéù tó jẹ́ olórí àwọn agbowó orí máa ń fipá gba owó lọ́wọ́ àwọn èèyàn, àmọ́ ó ronú pìwà dà, ó sì ṣèlérí pé òun máa dá àwọn owó náà pa dà

    • Iṣe 24:26, 27—Gómìnà Fẹ́líìsì ń retí pé kí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fún òun ní àbẹ̀tẹ́lẹ̀, àmọ́ Pọ́ọ̀lù ò fún un

Ìmutípara; ọtí àmujù

Owe 20:1; 23:20, 29-35; 1Kọ 5:11; 6:9, 10

Tún wo Ef 5:18; 1Ti 3:8; Tit 2:3; 1Pe 4:3

Tún wo “Ọtí Mímu”

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Jẹ 9:20-25—Hámù àti Kénáánì ọmọ ẹ̀ dẹ́ṣẹ̀ tó burú gan-an torí pé Nóà mutí yó

    • Da 5:1-6, 30—Ọba Bẹliṣásárì kú, ìjọba ẹ̀ sì dópin torí pé ó pẹ̀gàn Jèhófà nígbà tó mutí yó

Ìpànìyàn

Ẹk 20:13; Mt 15:19; 1Pe 4:15

Tún wo Mt 5:21, 22; Mk 7:21

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Jẹ 4:4-16—Dípò kí Kéènì gba ìmọ̀ràn onífẹ̀ẹ́ tí Jèhófà fún un, ńṣe ló pa arákùnrin ẹ̀ Ébẹ́lì tó jẹ́ olódodo

    • 1Ọb 21:1-26; 2Ọb 9:26—Torí pé Ọba Áhábù àti Ayaba Jésíbẹ́lì jẹ́ olójú kòkòrò tí wọ́n sì tún burú gan-an, wọ́n pa Nábótì àtàwọn ọmọ ẹ̀

Ìpínyà; ẹ̀ya ìsìn

Ro 16:17; Ga 5:19, 20; Tit 3:10, 11; 2Pe 2:1

Tún wo Iṣe 20:29, 30; 1Kọ 1:10-12; Ifi 2:6, 15

Irọ́; bíbanijẹ́

Wo “Irọ́”

Irọ́; kéèyàn máa tanni jẹ

Wo “Irọ́”

Ìwà àìnítìjú; ìwà àìmọ́; ìṣekúṣe; àgbèrè

Wo “Ìṣekúṣe”

Kéèyàn máa fa wàhálà; ìwà ipá

Sm 11:5; Owe 3:31; 29:22

Tún wo 1Ti 3:2, 3; Tit 1:7

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Ẹk 21:22-27—Òfin Mósè sọ pé kí wọ́n fìyà jẹ ẹnikẹ́ni tó bá hùwà ipá, tó sì ṣe ẹlòmíì léṣe tàbí tó pààyàn

Kéèyàn máa halẹ̀ mọ́ àwọn míì

Ef 6:9; 1Pe 2:23

Tún wo Sm 10:4, 7; 73:3, 8

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Iṣe 4:15-21—Ìgbìmọ̀ Sàhẹ́ndìrìn halẹ̀ mọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù torí wọn ò fẹ́ kí wọ́n máa wàásù mọ́

Kéèyàn máa kùn tàbí ráhùn

1Kọ 10:10; Flp 2:14; Jud 16

Tún wo Nọ 11:1

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Nọ 14:1-11, 26-30—Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń kùn sí Mósè àti Áárónì, àmọ́ lójú Jèhófà, òun gangan ni wọ́n ń kùn sí

    • Jo 6:41-69—Àwọn Júù kùn sí Jésù; àwọn kan lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ sì fi í sílẹ̀

Lílo ẹ̀jẹ̀ lọ́nà tí kò bá òfin Ọlọ́run mu

Jẹ 9:4; Di 12:16, 23; Iṣe 15:28, 29

Tún wo Le 3:17; 7:26

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 1Sa 14:32-34—Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì dẹ́ṣẹ̀ sí Jèhófà torí wọ́n jẹ ẹran láì da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀

Olè

Wo “Olè”

Ọ̀rọ̀ èébú

Mt 5:22; 1Kọ 6:9, 10; Ef 4:31

Tún wo Ẹk 22:28; Onw 10:20; Jud 8

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 2Sa 16:5-8; 1Ọb 2:8, 9, 44, 46—Ṣíméì pẹ̀gàn ẹni àmì òróró Jèhófà, ó sì jìyà ẹ̀

Ọ̀rọ̀ rírùn tàbí ẹ̀fẹ̀ rírùn

Ef 5:4; Kol 3:8

Tún wo Ef 4:29, 31

Sísọ̀rọ̀ àwọn èèyàn lẹ́yìn láìdáa; títojú bọ ọ̀rọ̀ ọlọ́rọ̀

Owe 25:23; 1Tẹ 4:11; 2Tẹ 3:11; 1Pe 4:15

Tún wo Owe 20:19; 1Ti 5:13

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́