Ṣé èèyàn lè wà láàyè títí láé?
Bíi Ti Orí Ìwé
	Kí ni ìdáhùn rẹ?
- Bẹ́ẹ̀ ni. 
- Bẹ́ẹ̀ kọ́. 
- Kò dá mi lójú. 
OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ
“Àwọn olódodo ni yóò jogún ayé, wọn yóò sì máa gbé inú rẹ̀ títí láé.”—SÁÀMÙ 37:29.
ÀǸFÀÀNÍ WO LÓ MÁA ṢE Ẹ́?
Inú ẹ á máa dùn, wàá sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ìdílé àtàwọn ọ̀rẹ́ rẹ.—JEREMÁYÀ 29:11.
Kì í ṣe àkókò díẹ̀ ni wàá fi gbádùn ayé ẹ, àmọ́ ńṣe ni wàá máa gbádùn ayé ẹ títí láé.—SÁÀMÙ 22:26.
ṢÉ O LÈ GBA OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ GBỌ́?
Bẹ́ẹ̀ ni! Tó o bá fẹ́ mọ ìdí tó fi yẹ kó o gba ohun tí Bíbélì sọ gbọ́, jọ̀ọ́ wo àwọn ẹ̀rí tó wà nínú ẹ̀kọ́ mẹ́ta tó wà nínú ìwé yìí. Àkòrí wọn ni: