ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w95 10/1 ojú ìwé 32
  • Nígbà Tí ‘Ẹ̀fúùfù Lè Gbéni Lọ Sí Ibikíbi’

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Nígbà Tí ‘Ẹ̀fúùfù Lè Gbéni Lọ Sí Ibikíbi’
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
w95 10/1 ojú ìwé 32

Nígbà Tí ‘Ẹ̀fúùfù Lè Gbéni Lọ Sí Ibikíbi’

“NÍGBÀ tí ẹnì kan kò bá mọ èbúté tí òun ń rè, ibikíbi ni ẹ̀fúùfù lè gbé e lọ.” Àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, tí a mọ̀ sí ti ọlọ́gbọ́n èrò orí ọ̀rúndún kìíní ti Romu, Lucius Annaeus Seneca, jẹ́rìí sí òtítọ́ tí a ti mọ̀ tipẹ́tipẹ́ náà pé: Kí ìgbèsí ayé tó lè ní ìdarísọ́nà, góńgó ṣe pàtàkì.

Bí ó ti wù kí ó rí, ní ọ̀pọ̀ ìgbà, ìgbésí ayé máa ń fì síhìn-ín sọ́hùn-ún láìní ìfojúsùn kankan. Kìkì yíyẹra fún gegele àti àjàyíká ìjì tí ó wà nínú ìgbésí ayé ojoojúmọ́ ti tẹ́ ọ̀pọ̀ lọ́rùn. Láìsí ohun gúnmọ́ kan pàtó lọ́kàn, wọ́n dà bí ìgbì òkun tí “ẹ̀fúùfù ń gbé síwá ní àkókò kan tí ó tún ń gbé sẹ́yìn ní àkókò mìíràn.” (Jakọbu 1:6, “Phillips”) Fún irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀, ‘ẹ̀fúùfù lè gbéni lọ sí ibikíbi.’

Bibeli pèsè àpẹẹrẹ àwọn tí wọ́n ní góńgó, tí wọ́n sì tipa báyìí ń ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni àwòfiṣàpẹẹrẹ fún àwọn Kristian lónìí. Mose “fi tọkàntara wo sísan èrè-ẹ̀san naa.” (Heberu 11:26) Paulu kọ̀wé pé: “Mo ń sáré tààràtà sí góńgó náà kí n baà lè jèrè ẹ̀bùn náà.” Ó gba àwọn onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ níyànjú láti “ní irú ìṣarasíhùwà kan náà.”—Filippi 3:14, 15, “Today’s English Version.”

Pẹ̀lú ojú wa tí a fi tọkàntara tẹ̀ mọ́ àwọn ìlérí Bibeli, ǹjẹ́ kí a máa fara wé ìgbàgbọ́ irú àwọn ọkùnrin tí wọ́n ní góńgó bẹ́ẹ̀.—Fi wé Heberu 13:7.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́