ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w96 10/15 ojú ìwé 3
  • Ìwàláàyè Ha Wà Lẹ́yìn Ikú Bí?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìwàláàyè Ha Wà Lẹ́yìn Ikú Bí?
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìbéèrè Ọlọ́jọ́ Pípẹ́
  • Gbígbé Àwọn Èrò Èké Nípa Ikú Yẹ̀ Wò
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
  • Ṣó Yẹ Kó O Máa Bẹ̀rù Àwọn Òkú?
    Jí!—2009
  • Kí Ló Ń Ṣẹlẹ̀ Sáwọn Tó Ti Kú?
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
  • Kí Ní Ń Ṣẹlẹ̀ sí Àwọn Olólùfẹ́ Wa Tí Wọ́n Ti Kú?
    Ìmọ̀ Tí Ń Sinni Lọ sí Ìyè Àìnípẹ̀kun
Àwọn Míì
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
w96 10/15 ojú ìwé 3

Ìwàláàyè Ha Wà Lẹ́yìn Ikú Bí?

FÚN ọ̀pọ̀ ẹgbẹ̀rúndún, ìbéèrè méjì ni ó ti ń pin aráyé lẹ́mìí: Èé ṣe tí a fi ní láti darúgbó, kí a sì kú lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn? Ìwàláàyè èyíkéyìí tí a ń nímọ̀lára rẹ̀ ha wà lẹ́yìn ikú bí?

Ọ̀pọ̀ ènìyàn ni ìbéèrè àkọ́kọ́ ti pin lẹ́mìí nítorí pé ìmọ̀ ìṣègùn sáyẹ́ǹsì pàápàá, pẹ̀lú gbogbo arabaríbí àwárí rẹ̀, kò tí ì lè pèsè ìdáhùn gúnmọ́ tàbí ìdáhùn tí ń tẹ́ni lọ́rùn.

Ọ̀pọ̀ yanturu ìdáhùn ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ti wà sí ìbéèrè kejì. Bí ó ti wù kí ó rí, ní gbogbogbòò, a wádìí ìdáhùn lórí bóyá ìwàláàyè tí a ń nímọ̀lára rẹ̀ ń bẹ lẹ́yìn ikú, lẹ́nu àwọn tí wọ́n sọ pé kì í ṣe ìwàláàyè yìí ni gbogbo ohun tí ó wà àti àwọn tí wọ́n rinkinkin mọ́ ọn bákan náà pé ìwàláàyè ń dópin nígbà ikú. Ọ̀pọ̀ nínú ẹgbẹ́ tí a mẹnu kàn kẹ́yìn yìí sọ fún wa pé ó dá àwọn lójú hán-ún-hán-ún pé ìwàláàyè kúkúrú tí ènìyàn ń ní ni gbogbo ohun tí ó lè fojú sọ́nà fún. Lọ́pọ̀ ìgbà, bí a bá jiyàn èyí, ìdáhùn àfigbera-ẹni-lẹ́sẹ̀ tí a máa ń rí gbà ni pé: “Ó dára, kò sí ẹni tí ó tí ì tibẹ̀ wá láti sọ fún wa, àbí ó wà?”

Bí ó ti máa ń ṣẹlẹ̀ nínú àwọn ìbéèrè míràn tí ń fa àríyànjiyàn, ọ̀pọ̀ ń bẹ tí wọn kò tí ì pinnu síbẹ̀—ní sísọ pé àwọ́n máa ń gbọ́ tìhín tọ̀hún lọ́nà kan tàbí òmíràn. Ṣùgbọ́n àwọn mìíràn yóò dáhùn, bóyá pẹ̀lú àìbìkítà pé: “A ní láti dúró di ìgbà tí àkókò yẹn bá dé!”

Ìbéèrè Ọlọ́jọ́ Pípẹ́

Ará Ìlà Oòrùn náà, Jóòbù, tí a mọ̀ bí ẹní mowó, tí ó gbajúmọ̀ nítorí sùúrù rẹ̀ lójú ìjìyà, ni ó gbé ìbéèrè àkọ́kọ́ dìde nípa ìwàláàyè lẹ́yìn ikú, ní nǹkan bí 3,500 ọdún sẹ́yìn. Jóòbù gbé ìbéèrè rẹ̀ kalẹ̀ lọ́nà yìí pé: “Ènìyàn kú, a sì sin ín; ó mí èémí rẹ̀ ìkẹyìn kò sì sí mọ́. Bí omí ti í pòórá nínú òkun tàbí bí ìsàlẹ̀ odò ti í yán tí í sì í gbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn dùbúlẹ̀ tí kò sì dìde . . . Bí ènìyàn bá kú, yóò ha tún wà láàyè bí?”—Jóòbù 14:10-14, New International Version.

Ṣùgbọ́n kì í ṣe Jóòbù nìkan ni ó béèrè ìbéèrè nípa ìwàláàyè lẹ́yìn ikú. Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ náà, Encyclopædia of Religion and Ethics, fúnni ní ìsọfúnni tí ń lani lóye yìí lábẹ́ àkòrí náà, “Ipò Tí Àwọn Òkú Wà,” pé: “Kò sí kókó ẹ̀kọ́ kan ní ìsopọ̀ pẹ̀lú ìwàláàyè ẹ̀dá tí ó ré kọjá ìmọ̀ rẹ̀, tí ó tí ì gba èrò inú ènìyàn pátápátá bíi ti ipò rẹ̀ lẹ́yìn ikú. [Àwọn ọmọ ìbílẹ̀] ní gbogbo ẹkùn ayé ní gbogbogbòò ní èrò ṣíṣe kedere, tí ó sì dájú hán-ún, nípa ayé ẹ̀mí—ìgbésí ayé tí ó wà níbẹ̀, àwọn ohun tí a fi lè dá a mọ̀ yàtọ̀, ìrísí ojú ilẹ̀ rẹ̀—èyí sì fi hàn bí kókó ẹ̀kọ́ náà ṣe jẹni lógún lọ́nà gíga tó. Ìbẹ̀rù tí ó tàn kálẹ̀ nípa àwọn òkú tọ́ka sí èrò àtijọ́ náà pé ìwàláàyè kò dópin sí ipò tí àwọn òkú wà. Ikú ti ké agbára kúrò; ìyẹ́n dájú ṣáká; ṣùgbọ́n àwọn agbára mìíràn kò ha wà lẹ́nu iṣẹ́, àbí àwọn agbára wọ̀nyẹn kò ha dáńgájíá láti fara hàn lọ́nà jíjáfáfá, tí ó sì lè yani lẹ́nu bí? Yálà àwọn ènìyàn kọ́kọ́ gbà gbọ́ pé ẹ̀mí, ọkàn, tàbí ẹ̀mí òkú, máa ń fi ara sílẹ̀, tàbí wọn kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ó dà bíi pé a ní ọ̀pọ̀ ìdí láti gbà gbọ́ pé wọ́n gbà pé àwọn òkú ṣì ń wà láàyè ní irú àwọn ọ̀nà kan.”

O lè jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìsọ̀rí mẹ́ta tí a mẹ́nu kàn lókè, ìyẹn ni pé: àwọn tí kò ní ìdánilójú nípa ohun tí ń ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ikú; àwọn tí wọ́n ní ìdánilójú pé irú ìwàláàyè kan ń bẹ lẹ́yìn ikú; tàbí àwọn tí wọ́n ní ìdánilójú pé ìwàláàyè yìí ni gbogbo ohun tí ó wà. Ohun yòó wù kí ọ̀ràn náà jẹ́, a ké sí ọ láti fara balẹ̀ ṣàyẹ̀wò ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ó tẹ̀ lé e. Wò ó bóyá ìwọ yóò rí ẹ̀rí dídánilójú tí ó bá Bíbélì mu nínú rẹ̀ pé ìfojúsọ́nà àgbàyanu fún ìgbésí ayé aláyọ̀ ń bẹ lẹ́yìn ikú, bí yóò ṣe wáyé, ibi tí yóò ti wáyé, àti ìgbà tí yóò wáyé.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́