ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb25 November ojú ìwé 2-3
  • November 3-9

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • November 3-9
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2025
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2025
mwb25 November ojú ìwé 2-3

NOVEMBER 3-9

ORIN SÓLÓMỌ́NÌ 1-2

Orin 132 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Ìtàn Nípa Ìfẹ́ Tí Kì Í Yẹ̀

(10 min.)

[Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Ohun Tó Wà Nínú Orin Sólómọ́nì.]

Sólómọ́nì sọ ọ̀rọ̀ tó dùn fún ọ̀dọ́bìnrin Ṣúlámáítì, ó sì ṣèlérí pé òun máa fún un ní ọ̀pọ̀ nǹkan (Sol 1:9-11)

Ọ̀dọ́bìnrin Ṣúlámáítì ní ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ sí olólùfẹ́ rẹ̀ tó jẹ́ olùṣọ́ àgùntàn, ìyẹn ló mú kó jẹ́ olóòótọ́ sí i (Sol 2:16, 17; w15 1/15 30 ¶9-10)

Ọba Sólómọ́nì sọ fún ọ̀dọ́bìnrin Ṣúlámáítì pé kó wá sínú àgọ́ òun, àmọ́ ọ̀dọ́bìnrin náà kọ̀, ó kẹ̀yìn sí i, ó sì káwọ́ gbera. Mẹ́ta lára àwọn ìránṣẹ́ Sólómọ́nì dúró síwájú àgọ́ náà, wọ́n gbé aṣọ ìnura, bàsíà àti ìgò omi dání.

ÀBÁ: Nínú Bíbélì Ìtumọ̀ Ayé Tuntun, apá tá a pè ní “Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Yìí” máa ń wà níbẹ̀rẹ̀ ìwé Bíbélì kọ̀ọ̀kan. Lo apá yìí tó o bá ń ka ìwé Orin Sólómọ́nì kó o lè mọ ẹni tó ń sọ̀rọ̀ gan-an.

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sol 2:7—Ẹ̀kọ́ wo ni àwọn Kristẹni tí kò tíì ṣègbéyàwó lè kọ́ lára ọ̀dọ́bìnrin Ṣúlámáítì? (w15 1/15 31 ¶11)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

(4 min.) Sol 2:1-17 (th ẹ̀kọ́ 12)

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(3 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Lo ọ̀kan nínú àwọn àkòrí tó wà ní àfikún A nínú ìwé Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Èèyàn láti bá ẹni náà sọ̀rọ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 1 kókó 3)

5. Pa Dà Lọ

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Lo ọ̀kan nínú àwọn àkòrí tó wà ní àfikún A nínú ìwé Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Èèyàn láti bá ẹni náà sọ̀rọ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 9 kókó 3)

6. Sọ Àwọn Èèyàn Di Ọmọ Ẹ̀yìn

(5 min.) lff ẹ̀kọ́ 18 ọ̀rọ̀ ìbẹ̀rẹ̀ àti kókó 1-3 (th ẹ̀kọ́ 8)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 46

7. ‘Ẹni Tó Lawọ́ Máa Gba Ìbùkún’

(15 min.) Alàgbà ni kó ṣe iṣẹ́ yìí.

Tá a bá ń lo àkókò wa, okun wa àtàwọn nǹkan tá a ní láti ran àwọn èèyàn lọ́wọ́, Jèhófà máa bù kún wa. Ohun kan ni pé, inú ẹni tá a ràn lọ́wọ́ máa dùn gan-an, àwa náà sì máa láyọ̀. (Owe 22:9) Tá a bá ń fúnni, a máa láyọ̀ kì í ṣe torí pé à ń fara wé Jèhófà nìkan, àmọ́ torí pé a tún máa rí ojú rere ẹ̀.—Owe 19:17; Jem 1:17.

Ọmọbìnrin kékeré kan ń fi owó sínú àpótí ọrẹ.
Ọkùnrin kan ń fi tablet ẹ̀ ṣètò bí á ṣe máa fi owó ṣètìlẹyìn lóṣooṣù.

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ A Máa Láyọ̀ Tá A Bá Ń Fúnni. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

  • Báwo ni ìtìlẹyìn tí àwọn ará wa kárí ayé ṣe ṣe jẹ́ káwọn ará tá a rí nínú fídíò yẹn láyọ̀?

  • Báwo ni àwọn ará tá a ràn lọ́wọ́ ṣe rí ayọ̀ nígbà táwọn náà ran àwọn míì lọ́wọ́?

Mọ Púpọ̀ Sí I Lórí Ìkànnì

Àmì “Ọrẹ“ tó jẹ́ ọwọ́ tó mówó dání.

Àwọn ọ̀nà wo lo lè gbà fowó ṣètìlẹyìn fún iṣẹ́ táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń ṣe kárí ayé? Tẹ ìlujá “Donations” tó wà nísàlẹ̀ ibi tó o máa kọ́kọ́ rí tó o bá ṣí JW Library. Ní ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè, wàá rí ìlujá kan tá a pè ní FAQ, ìyẹn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Máa Ń Béèrè. Tó o bá tẹ̀ ẹ́, á gbé àpilẹ̀kọ kan jáde tá a pè ní Donations to Jehovah’s Witnesses—Frequently Asked Questions.

8. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) lfb ẹ̀kọ́ 32-33

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 137 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́