ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • ijwfq àpilẹ̀kọ 16
  • Ṣé Torí Kẹ́ Ẹ Lè Jèrè Ìgbàlà Lẹ Ṣe Ń Wàásù Látilé Délé?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ṣé Torí Kẹ́ Ẹ Lè Jèrè Ìgbàlà Lẹ Ṣe Ń Wàásù Látilé Délé?
  • Àwọn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Sábà Máa Ń Béèrè Nípa Ẹlẹ́rìí Jèhófà
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Jẹ́ Kí “Ìrètí Ìgbàlà” Wà Lọ́kàn Rẹ Digbí!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
  • Kí Ni Ìgbàlà?
    Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Róòmù 6:23—“Ikú ni Èrè Ẹ̀ṣẹ̀, Ṣùgbọ́n Ẹ̀bùn Ọlọ́run ni Ìyè Àìnípẹ̀kun Nínú Kristi Jesu Olúwa Wa”
    Àlàyé Àwọn Ẹsẹ Bíbélì
  • Kí Nìdí Tí Ẹ̀bùn Yìí Fi Ṣe Iyebíye Gan-an?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2017
Àwọn Míì
Àwọn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Sábà Máa Ń Béèrè Nípa Ẹlẹ́rìí Jèhófà
ijwfq àpilẹ̀kọ 16

Ṣé Torí Kẹ́ Ẹ Lè Jèrè Ìgbàlà Lẹ Ṣe Ń Wàásù Látilé Délé?

Rárá. A máa ń ṣiṣẹ́ ìwàásù ilé-dé-ilé o, àmọ́ a ò gbà pé tá a bá ti ń wàásù, a ti lẹ́tọ̀ọ́ sí ìgbàlà nìyẹn. (Éfésù 2:8) Kí nìdí?

Jẹ́ ká fi wé ohun kan: Ká sọ pé ọkùnrin olówó tí ń fowó ṣàánú kan sọ pé òun máa fún gbogbo ẹni tó bá wá sí ibì kan lọ́jọ́ báyìí-báyìí lẹ́bùn iyebíye kan. Tó o bá gbà pé òótọ́ lẹni yẹn ń sọ, ṣó ò ní ṣe ohun tó ní káwọn èèyàn ṣe yẹn? Ó dájú pé wàá ṣe bẹ́ẹ̀! Wàá tún fẹ́ sọ fáwọn ọ̀rẹ́ rẹ àti ìbátan rẹ nípa àǹfààní tó yọjú yẹn káwọn náà bàa lè jẹ nínú rẹ̀. Síbẹ̀ náà, torí pé o ṣe ohun tí ọkùnrin yẹn ni kó o ṣe kọ́ lo fi dẹni tó lẹ́tọ̀ọ́ sí ẹ̀bùn. Ńṣe ló fi ẹ̀bùn yẹn ta ọ́ lọ́rẹ.

Bákan náà, àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà gba ìlérí Ọlọ́run gbọ́ pé gbogbo àwọn tó bá ṣègbọ́ràn sí i yóò rí ìyè àìnípẹ̀kun. (Róòmù 6:23) A máa ń fẹ́ sọ ohun tá a gbà gbọ́ yìí fáwọn èèyàn, nírètí pé àwọn náà máa rí ìmúṣẹ ìlérí Ọlọ́run gbà. Àmọ́ a ò gbà pé iṣẹ́ ìwàásù ló máa jẹ́ ká lẹ́tọ̀ọ́ sí ìgbàlà. (Róòmù 1:17; 3:28) Ká sòótọ́, kò sóhun tẹ́dàá èèyàn kankan lè ṣe tó fi lè lẹ́tọ̀ọ́ sí ẹ̀bùn àgbàyanu yẹn látọ̀dọ̀ Ọlọ́run. “Kì í ṣe ntori iṣẹ́ rere kan tí a ṣe, ṣugbọn nitori àánú rẹ̀ ni ó fi gbà wá là.”—Títù 3:5, Ìròhìn Ayọ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́