ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • ijwbq àpilẹ̀kọ 128
  • Ṣé Pọ́gátórì Wà Nínú Bíbélì?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ṣé Pọ́gátórì Wà Nínú Bíbélì?
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun tí Bíbélì sọ
  • Ǹjẹ́ O Lè Gba Bíbélì Gbọ́?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1998
  • Ikú
    Jí!—2014
  • Ǹjẹ́ O Lè Ran Àwọn Òkú Lọ́wọ́?
    Jí!—2006
  • Kí Ní Ń Ṣẹlẹ̀ sí Ọkàn Nígbà Ikú?
    Kí Ní Ṣẹlẹ̀ sí Wa Nígbà Tí A Bá Kú?
Ohun Tí Bíbélì Sọ
ijwbq àpilẹ̀kọ 128
Ayàwòrán kan yàwòrán bó ṣe rò pé pọ́gátórì rí

Ṣé Pọ́gátórì Wà Nínú Bíbélì?

Ohun tí Bíbélì sọ

Rárá, kò sí níbẹ̀. A ò lè rí ọ̀rọ̀ náà, “pọ́gátórì” nínú Bíbélì, Bíbélì ò sì fi kọ́ni pé a máa ń yọ́ ọkàn àwọn tó ti kú mọ́ ní pọ́gátórì.a Wo ohun tí Bíbélì sọ nípa ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú, àti bí ohun tó sọ ṣe ta ko ẹ̀kọ́ pọ́gátórì.

  • Ìgbàgbọ́ nínú ẹ̀jẹ̀ Jésù ló máa ń wẹ èèyàn mọ́ nínú ẹ̀ṣẹ̀, kì í ṣe pọ́gátórì. Bíbélì sọ pé “ẹ̀jẹ̀ Jésù Ọmọ [Ọlọ́run] . . . ń wẹ̀ wá mọ́ kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀” àti pé “Jésù Kristi . . . dá wa nídè kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa.” (1 Jòhánù 1:7; Ìṣípayá 1:5, Bibeli Ìròyìn Ayọ̀) Jésù fi “ẹ̀mí rẹ̀ ṣe ìràpadà fún ọpọlọpọ eniyan” láti gbà wọ́n kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.​—Mátíù 20:28, Bibeli Ìròyìn Ayọ̀.

  • Àwọn tó ti kú kò mọ nǹkan mọ́. “Nítorí alààyè mọ̀ pé òun óo kú, ṣugbọn òkú kò mọ nǹkankan mọ́.” (Oníwàásù 9:5, Bibeli Ìròyìn Ayọ̀) Ẹni tó ti kú ò lè mọ nǹkan kan lára, torí náà, kò sí nǹkan tó ń jẹ́ pé iná pọ́gátórì kan ń yọ́ ẹni tó ti kú mọ́.

  • Téèyàn bá ti kú, ó ti jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ nìyẹn. Bíbélì sọ pé “ikú ni èrè ẹ̀ṣẹ̀” àti pé “ẹni tí ó ti kú ti bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀.” (Róòmù 6:7, 23, Bibeli Ìròyìn Ayọ̀) Ikú ni èrè ẹ̀ṣẹ̀, téèyàn bá ti kú, ó ti jìyà àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ nìyẹn.

Kí ni wọ́n ń pè ní pọ́gátórì?

Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì sọ pé pọ́gátórì jẹ́ ipò tàbí ibi tí àwọn tó ti kú wà, tí ọkàn wọn ti máa ń ṣe ètùtù fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí kò tíì rí ìdáríjì, táá sì yọ́ wọn mọ́.b Ìwé Catechism of the Catholic Church sọ pé ìyọ́mọ́ yìí ṣe pàtàkì “kí èèyàn lè wà ní mímọ́, kó bàa lè rí ọ̀run wọ̀, níbi táá ti máa yọ̀.” Ìwé Catechism fi kún un pé, “Ṣọ́ọ̀ṣì fi kọ́ni látinú àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ wọn . . . pé iná kan wà tó ń yọ́ni mọ́,” bó ṣe wà nínú àwòrán tó wà nínú àpilẹ̀kọ yìí. Àmọ́ ẹ̀kọ́ yìí ò bá Ìwé Mímọ́ mu.

Ibo ni ẹ̀kọ́ pọ́gátórì ti ṣẹ̀ wá?

wọn Gíríìkì àtijọ́ gbà pé ibì kan wà tó ń jẹ́ Limbo, táwọn òkú máa ń lọ, wọ́n sì gbà gbọ́ nínú pọ́gátórì. Ọ̀gbẹ́ni kan tí wọ́n ń pè ní Clement of Alexandria sọ pé òótọ́ ni pé iná tó ń yọ́ni mọ́ lè wẹ àwọn òkú mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn, bó tiẹ̀ jẹ́ pé ìmọ̀ èrò orí àwọn Gíríìkì ló ń tẹ̀ lé. Àmọ́ bí ìwé The History of Christian Doctrines ṣe sọ, Póòpù Gregory Ńlá gangan ló tẹnu mọ́ ọn pé òótọ́ tí kò ṣeé já ní koro lọ̀rọ̀ iná pọ́gátórì. Ìwé yìí tún fi kún un pé Gregory, tó jẹ́ póòpù látọdún 590 sí 604 Sànmánì Kristẹni, “ni wọ́n sábà máa ń pè ní ‘ẹni tó fìdí ẹ̀kọ́ pọ́gátórì sọlẹ̀.’” Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì ṣàlàyé ohun tí ẹ̀kọ́ pọ́gátórì tí wọ́n fi ń kọ́ni túmọ̀ sí níbi àwọn ìpàdé àpérò tí wọ́n ṣe, ìyẹn ìpàdé Council of Lyons (ti ọdún 1274) àti Council of Florence (ti ọdún 1439), wọ́n sì tún un sọ níbi ìpàdé Council of Trent lọ́dún 1547.

a Ìwé Orpheus: A General History of Religions sọ̀rọ̀ nípa pọ́gátórì, ó ní “kò sírú ọ̀rọ̀ yẹn nínú àwọn ìwé Ìhìn Rere.” Bákan náà, ìwé gbédègbẹ́yọ̀ New Catholic Encyclopedia sọ pé: “Ibi tá a parí èrò sí ni pé, ọ̀rọ̀ pọ́gátórì tí Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì fi ń kọ́ni kò sí nínú Ìwé Mímọ́, inú àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ ló ti wá.”​—Ẹ̀dà Kejì, Ìdìpọ̀ 11, ojú ìwé 825.

b Wo ìwé gbédègbẹ́yọ̀ New Catholic Encyclopedia, Ẹ̀dà Kejì, Ìdìpọ̀ 11, ojú ìwé 824.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́