ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w97 5/15 ojú ìwé 29
  • “Wọ́n Ń Fi Ohun Tí Ẹ̀sìn Wọn Kọ́ Wọn Sílò”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Wọ́n Ń Fi Ohun Tí Ẹ̀sìn Wọn Kọ́ Wọn Sílò”
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ‘Inú Rere àti Ìṣòtítọ́ Tẹ́nì Kan Fi Hàn’
    Ìrírí Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà
  • ‘A Ń Fẹ́ Àwọn Aláìlábòsí’
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
w97 5/15 ojú ìwé 29

“Wọ́n Ń Fi Ohun Tí Ẹ̀sìn Wọn Kọ́ Wọn Sílò”

OBÌNRIN kan láti Miami, Florida, U.S.A., fi lẹ́tà tí ó tẹ̀ lé e yìí ránṣẹ́ sí ilé iṣẹ́ agbéròyìnjáde kan: “Ní ọjọ́ 10 oṣù Dec., wọ́n yọ pọ́ọ̀sì ọmọkùnrin mi mọ́ ọn lára ní ọjà ẹrù tòkunbọ̀ kan. Ìwé ìwakọ̀ rẹ̀, káàdì Ètò Ìpèsè Ìrànwọ́ fún Ọjọ́ Ogbó, àti oríṣiríṣi nǹkan mìírán wà nínú rẹ̀, pẹ̀lú 260 dọ́là.

“Lẹ́yìn tí ó ti fi ọ̀rọ̀ náà tó máníjà létí, ó pa dà wá sílé. Ní ọwọ́ ìrọ̀lẹ́, obìnrin kan tí ń sọ èdè Spanish tí alámòójútó [tẹlifóònù] ṣe ògbufọ̀ fún, tẹ̀ ẹ́ láago, ó sì sọ fún un pé òun ti bá a rí pọ́ọ̀sì rẹ̀.

“Obìnrin náà sọ àdírẹ́sì rẹ̀ fún un. . . . Ó fún un ní pọ́ọ̀sì náà, èyí tí ó ṣì wà bí ó ṣe wà tẹ́lẹ̀, títí kan 260 dọ́là tí ó wà nínú rẹ̀.

“Ó rí jáwójáwó náà nígbà tí ó ń yọ pọ́ọ̀sì náà, ó sì kígbe. Jáwójáwó náà ju pọ́ọ̀sì náà sílẹ̀, ó sì fẹsẹ̀ fẹ́ẹ. Nígbà tí yóò fi bojú wòkè kò rí ọmọkùnrin mi mọ́, nítorí náà, ó mú pọ́ọ̀sì náà lọ sílé ó sì tẹ ọmọkùnrin mi láago.

“Ẹlẹ́rìí Jèhófà ni ọmọbìnrin náà àti ìdílé rẹ̀. Ó hàn gbangba gbàǹgbà pé wọ́n ń fi ohun tí ẹ̀sìn wọn kọ́ wọn sílò.”

Kì í ṣe nítorí kí àwọn ènìyàn baà lè yìn wọ́n ni Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ń fi ìwà àìlábòsí hàn. (Éfésù 6:7) Kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n fẹ́ láti fi tọkàntọkàn mú ìyìn wá fún Bàbá wọn ọ̀run, Jèhófà. (Kọ́ríńtì Kíní 10:31) Ìfẹ́ wọn fún Ọlọ́run àti fún àwọn aládùúgbò wọn ń sún wọn láti polongo “ìhìn rere” Ìjọba Ọlọ́run. (Mátíù 24:14) Nípasẹ̀ Ìjọba náà, Ọlọ́run ṣèlérí láti sọ ilẹ̀ ayé di párádísè ẹlẹ́wà kan. Nígbà náà, ilẹ̀ ayé kì yóò jẹ́ ibi ẹlẹ́wà tí a lè fojú rí nìkan, ṣùgbọ́n yóò tún jẹ́ ibi tí ìwà rere títayọ wà, ibi tí àìlábòsí yóò ti gbilẹ̀ títí láé.—Hébérù 13:18; Pétérù Kejì 3:13.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́