ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2026)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Sunday, October 12

[Jèhófà] máa fún yín lókun, ó máa sọ yín di alágbára, ó sì máa fẹsẹ̀ yín múlẹ̀ gbọn-in.—1 Pét. 5:10.

Bíbélì sábà máa ń sọ pé àwọn olóòótọ́ èèyàn ní ìgbàgbọ́ tó lágbára. Àmọ́ kì í ṣe gbogbo ìgbà lẹni tó nígbàgbọ́ jù lára wọn máa ń rò pé òun lágbára. Bí àpẹẹrẹ, Ọba Dáfídì sọ pé òun “lágbára bí òkè,” àmọ́ nígbà kan, ó tún sọ pé “jìnnìjìnnì bá mi.” (Sm. 30:7) Sámúsìn ní agbára tó ṣàrà ọ̀tọ̀ nígbà tí ẹ̀mí Ọlọ́run fún un lókun, síbẹ̀ ó mọ̀ pé láìsí agbára tí Ọlọ́run fún òun, òun ‘ò ní lókun mọ́, òun ò sì ní yàtọ̀ sí gbogbo ọkùnrin yòókù.’ (Oníd. 14:​5, 6; 16:17) Agbára tí Jèhófà fún àwọn ọkùnrin olóòótọ́ yẹn ló jẹ́ kí wọ́n lókun. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù náà gbà pé òun nílò agbára látọ̀dọ̀ Jèhófà. (2 Kọ́r. 12:​9, 10) Ó ní àìsàn tó ń bá a fínra. (Gál. 4:​13, 14) Nígbà míì, kì í rọrùn fún un láti ṣe ohun tó tọ́. (Róòmù 7:​18, 19) Yàtọ̀ síyẹn, ìdààmú máa ń bá a torí kò mọ ohun tó lè ṣẹlẹ̀ sóun. (2 Kọ́r. 1:​8, 9) Síbẹ̀ nígbà tí Pọ́ọ̀lù jẹ́ aláìlera, ó di alágbára. Lọ́nà wo? Jèhófà ló fún Pọ́ọ̀lù lágbára tó nílò. Òun ló sì fún un lókun. w23.10 12 ¶1-2

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Monday, October 13

Jèhófà ń rí ohun tó wà nínú ọkàn.—1 Sám. 16:7.

Tó bá ń ṣe wá nígbà míì bíi pé a ò já mọ́ nǹkan kan, ẹ jẹ́ ká máa rántí pé Jèhófà fúnra ẹ̀ ló fà wá sọ́dọ̀ ara ẹ̀. (Jòh. 6:44) Ó ń rí àwọn ànímọ́ dáadáa tá a ní táwa lè má rí, ó sì mọ ohun tó wà lọ́kàn wa. (2 Kíró. 6:30) Torí náà, ó yẹ ká gbà pé òótọ́ ni Jèhófà sọ nígbà tó sọ pé a ṣeyebíye lójú òun. (1 Jòh. 3:​19, 20) Ká tó kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́, àwọn kan lára wa ti ṣe àwọn nǹkan kan tá a ṣì ń kábàámọ̀ ẹ̀ báyìí. (1 Pét. 4:3) Àwọn Kristẹni olóòótọ́ kan náà máa ń ní ẹ̀dùn ọkàn torí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n dá. Ìwọ ńkọ́, ṣé ó máa ń ṣe ẹ́ bíi pé Jèhófà ò lè dárí jì ẹ́? Tó bá rí bẹ́ẹ̀, jẹ́ kọ́kàn ẹ balẹ̀ torí pé ó ti ṣe àwọn olóòótọ́ ìránṣẹ́ Jèhófà kan bẹ́ẹ̀ rí. Bí àpẹẹrẹ, ẹ̀dùn ọkàn máa ń bá àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù gan-an tó bá ń rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá sẹ́yìn. (Róòmù 7:24) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Pọ́ọ̀lù ti ronú pìwà dà àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ̀, ó sì ti ṣèrìbọmi. Síbẹ̀, ó sọ pé òun lòun “kéré jù nínú àwọn àpọ́sítélì,” òun sì ni “ẹni àkọ́kọ́” nínú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.—1 Kọ́r. 15:9; 1 Tím. 1:15. w24.03 27 ¶5-6

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Tuesday, October 14

Wọ́n fi ilé Jèhófà sílẹ̀.—2 Kíró. 24:18.

Ohun tá a rí kọ́ nínú ìpinnu tí ò dáa tí Ọba Jèhóáṣì ṣe ni pé ó yẹ ká yan àwọn ọ̀rẹ́ táá jẹ́ ká níwà rere, ìyẹn àwọn ọ̀rẹ́ tó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, tí wọ́n sì ń múnú ẹ̀ dùn. Kì í ṣe àwọn tá a jọ jẹ́ ẹgbẹ́ nìkan la lè yàn lọ́rẹ̀ẹ́, a tún lè yan àwọn tó dàgbà jù wá lọ tàbí àwọn tó kéré sí wa. Ẹ má gbàgbé pé Jèhóáṣì kéré gan-an sí ọ̀rẹ́ rẹ̀ Jèhóádà. Tó o bá fẹ́ yan ọ̀rẹ́, bi ara ẹ láwọn ìbéèrè yìí: ‘Ṣé àwọn tí mo fẹ́ yàn lọ́rẹ̀ẹ́ yìí máa jẹ́ kí ìgbàgbọ́ mi nínú Jèhófà túbọ̀ lágbára? Ṣé wọ́n á jẹ́ kí n máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà Ọlọ́run? Ṣé wọ́n máa ń sọ̀rọ̀ nípa Jèhófà àti òtítọ́ tó ń kọ́ wa? Ṣé wọ́n máa ń tẹ̀ lé ìlànà Ọlọ́run? Ṣé wọ́n máa ń bá mi sòótọ́ ọ̀rọ̀ tí mo bá ṣohun tí ò dáa àbí ńṣe ni wọ́n máa ń sọ pé ohun tí mo ṣe dáa?’ (Òwe 27:​5, 6, 17) Ká sòótọ́, táwọn ọ̀rẹ́ ẹ ò bá nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, kò yẹ kó o máa bá wọn rìn. Àmọ́ tó o bá láwọn ọ̀rẹ́ tó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, àwọn ọ̀rẹ́ gidi nìyẹn. Má fi wọ́n sílẹ̀ o!—Òwe 13:20. w23.09 9-10 ¶6-7

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́