ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2026)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Friday, October 17

Ẹ máa rìn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìmọ́lẹ̀.—Éfé. 5:8.

Ó ṣe pàtàkì pé kí ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run ràn wá lọ́wọ́ tá a bá fẹ́ jẹ́ “ọmọ ìmọ́lẹ̀.” Kí nìdí? Ìdí ni pé kò rọrùn láti jẹ́ oníwà mímọ́ nínú ayé tó kún fún ìṣekúṣe yìí. (1 Tẹs. 4:​3-5, 7, 8) Ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run lè ràn wá lọ́wọ́ láti borí èrò burúkú tí ayé ń gbé lárugẹ, títí kan àwọn ọgbọ́n orí èèyàn àtàwọn èrò tí ò bá ìlànà Ọlọ́run mu. Yàtọ̀ síyẹn, ẹ̀mí mímọ́ tún máa jẹ́ ká ní “oríṣiríṣi ohun rere àti òdodo.” (Éfé. 5:9) Báwo la ṣe lè rí ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run gbà? Ọ̀nà kan tá a lè gbà ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé ká máa gbàdúrà pé kí Jèhófà fún wa. Jésù sọ pé Jèhófà “máa fi ẹ̀mí mímọ́ fún àwọn tó ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.” (Lúùkù 11:13) Yàtọ̀ síyẹn, a tún máa ń rí ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run gbà tá a bá ń yin Jèhófà pẹ̀lú àwọn ará nípàdé. (Éfé. 5:​19, 20) Torí náà, ẹ̀mí mímọ́ máa jẹ́ ká láwọn ìwà táá jẹ́ ká máa múnú Ọlọ́run dùn. w24.03 23-24 ¶13-15

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Saturday, October 18

Ẹ máa béèrè, a sì máa fún yín; ẹ máa wá kiri, ẹ sì máa rí; ẹ máa kan ilẹ̀kùn, a sì máa ṣí i fún yín.—Lúùkù 11:9.

Ṣé o rò pé ó yẹ kó o túbọ̀ máa ní sùúrù? Tó bá rí bẹ́ẹ̀, gbàdúrà nípa ẹ̀. Sùúrù wà lára ìwà tí ẹ̀mí Ọlọ́run máa ń jẹ́ ká ní. (Gál. 5:​22, 23) Torí náà, a lè gbàdúrà pé kí Jèhófà fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀, kó sì ràn wá lọ́wọ́ ká lè ní àwọn ìwà yẹn. Tí nǹkan kan bá ṣẹlẹ̀ tó múnú bí wa, ó yẹ ká “máa béèrè” lọ́wọ́ Jèhófà pé kó fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀ ká lè ní sùúrù. (Lúùkù 11:13) A tún lè bẹ Jèhófà pé kó jẹ́ ká máa ní sùúrù bíi tiẹ̀. Lẹ́yìn tá a bá gbàdúrà pé kí Jèhófà ṣe àwọn nǹkan yìí fún wa, ó yẹ ká ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe láti máa ní sùúrù lójoojúmọ́. Tá a bá túbọ̀ ń gbàdúrà pé kí Jèhófà jẹ́ ká máa ní sùúrù, tá a sì ń sapá láti ṣe bẹ́ẹ̀, Jèhófà máa ràn wá lọ́wọ́ ká lè jẹ́ onísùúrù, kódà tó bá jẹ́ pé a ò kì í ṣe bẹ́ẹ̀ tẹ́lẹ̀. Ohun míì tó máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ ni pé kó o máa ṣàṣàrò lórí àwọn àpẹẹrẹ inú Bíbélì. Ọ̀pọ̀ àpẹẹrẹ àwọn tó ní sùúrù ló wà nínú Bíbélì. Tá a bá ṣàṣàrò lórí àwọn àpẹẹrẹ yẹn, àá kẹ́kọ̀ọ́ lára wọn, àá sì mọ bó ṣe yẹ káwa náà máa ní sùúrù. w23.08 22-23 ¶10-11

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Sunday, October 19

Ẹ rọ àwọ̀n yín sísàlẹ̀ láti kó ẹja.—Lúùkù 5:4.

Jésù fi dá àpọ́sítélì Pétérù lójú pé Jèhófà máa bójú tó o. Lẹ́yìn tí Jésù jíǹde, ó jẹ́ kí Pétérù àtàwọn àpọ́sítélì yòókù rí ẹja pa lọ́nà ìyanu. (Jòh. 21:​4-6) Iṣẹ́ ìyanu yìí jẹ́ kó túbọ̀ dá Pétérù lójú pé Jèhófà máa pèsè àwọn ohun tó nílò. Ó ṣeé ṣe kí Pétérù rántí ohun tí Jésù sọ pé Jèhófà máa pèsè fún àwọn tó bá ń ‘wá Ìjọba náà lákọ̀ọ́kọ́.’ (Mát. 6:33) Torí náà, iṣẹ́ ìwàásù ni Pétérù gbájú mọ́, kì í ṣe iṣẹ́ ẹja pípa. Ó fi ìgboyà sọ̀rọ̀ níwájú ọ̀pọ̀ èèyàn lọ́jọ́ Pẹ́ńtíkọ́sì 33 S.K., ìyẹn sì jẹ́ kí wọ́n di ọmọ ẹ̀yìn. (Ìṣe 2:​14, 37-41) Lẹ́yìn náà, ó tún ran àwọn ará Samáríà àtàwọn tí kì í ṣe Júù lọ́wọ́ láti di ọmọ ẹ̀yìn Kristi. (Ìṣe 8:​14-17; 10:​44-48) Ó dájú pé Jèhófà lo Pétérù lọ́nà àrà ọ̀tọ̀ láti ran onírúurú èèyàn lọ́wọ́, kí wọ́n lè dara pọ̀ mọ́ ìjọ Kristẹni. w23.09 20 ¶1; 23 ¶11

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́