ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2026)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Saturday, October 18

Ẹ máa béèrè, a sì máa fún yín; ẹ máa wá kiri, ẹ sì máa rí; ẹ máa kan ilẹ̀kùn, a sì máa ṣí i fún yín.—Lúùkù 11:9.

Ṣé o rò pé ó yẹ kó o túbọ̀ máa ní sùúrù? Tó bá rí bẹ́ẹ̀, gbàdúrà nípa ẹ̀. Sùúrù wà lára ìwà tí ẹ̀mí Ọlọ́run máa ń jẹ́ ká ní. (Gál. 5:​22, 23) Torí náà, a lè gbàdúrà pé kí Jèhófà fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀, kó sì ràn wá lọ́wọ́ ká lè ní àwọn ìwà yẹn. Tí nǹkan kan bá ṣẹlẹ̀ tó múnú bí wa, ó yẹ ká “máa béèrè” lọ́wọ́ Jèhófà pé kó fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀ ká lè ní sùúrù. (Lúùkù 11:13) A tún lè bẹ Jèhófà pé kó jẹ́ ká máa ní sùúrù bíi tiẹ̀. Lẹ́yìn tá a bá gbàdúrà pé kí Jèhófà ṣe àwọn nǹkan yìí fún wa, ó yẹ ká ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe láti máa ní sùúrù lójoojúmọ́. Tá a bá túbọ̀ ń gbàdúrà pé kí Jèhófà jẹ́ ká máa ní sùúrù, tá a sì ń sapá láti ṣe bẹ́ẹ̀, Jèhófà máa ràn wá lọ́wọ́ ká lè jẹ́ onísùúrù, kódà tó bá jẹ́ pé a ò kì í ṣe bẹ́ẹ̀ tẹ́lẹ̀. Ohun míì tó máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ ni pé kó o máa ṣàṣàrò lórí àwọn àpẹẹrẹ inú Bíbélì. Ọ̀pọ̀ àpẹẹrẹ àwọn tó ní sùúrù ló wà nínú Bíbélì. Tá a bá ṣàṣàrò lórí àwọn àpẹẹrẹ yẹn, àá kẹ́kọ̀ọ́ lára wọn, àá sì mọ bó ṣe yẹ káwa náà máa ní sùúrù. w23.08 22-23 ¶10-11

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Sunday, October 19

Ẹ rọ àwọ̀n yín sísàlẹ̀ láti kó ẹja.—Lúùkù 5:4.

Jésù fi dá àpọ́sítélì Pétérù lójú pé Jèhófà máa bójú tó o. Lẹ́yìn tí Jésù jíǹde, ó jẹ́ kí Pétérù àtàwọn àpọ́sítélì yòókù rí ẹja pa lọ́nà ìyanu. (Jòh. 21:​4-6) Iṣẹ́ ìyanu yìí jẹ́ kó túbọ̀ dá Pétérù lójú pé Jèhófà máa pèsè àwọn ohun tó nílò. Ó ṣeé ṣe kí Pétérù rántí ohun tí Jésù sọ pé Jèhófà máa pèsè fún àwọn tó bá ń ‘wá Ìjọba náà lákọ̀ọ́kọ́.’ (Mát. 6:33) Torí náà, iṣẹ́ ìwàásù ni Pétérù gbájú mọ́, kì í ṣe iṣẹ́ ẹja pípa. Ó fi ìgboyà sọ̀rọ̀ níwájú ọ̀pọ̀ èèyàn lọ́jọ́ Pẹ́ńtíkọ́sì 33 S.K., ìyẹn sì jẹ́ kí wọ́n di ọmọ ẹ̀yìn. (Ìṣe 2:​14, 37-41) Lẹ́yìn náà, ó tún ran àwọn ará Samáríà àtàwọn tí kì í ṣe Júù lọ́wọ́ láti di ọmọ ẹ̀yìn Kristi. (Ìṣe 8:​14-17; 10:​44-48) Ó dájú pé Jèhófà lo Pétérù lọ́nà àrà ọ̀tọ̀ láti ran onírúurú èèyàn lọ́wọ́, kí wọ́n lè dara pọ̀ mọ́ ìjọ Kristẹni. w23.09 20 ¶1; 23 ¶11

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Monday, October 20

Tí ẹ ò bá sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, a máa gé yín sí wẹ́wẹ́.—Dán. 2:5.

Nǹkan bí ọdún méjì lẹ́yìn táwọn ará Bábílónì pa Jerúsálẹ́mù run, Nebukadinésárì ọba Bábílónì lá àlá kan tó bani lẹ́rù. Nínú àlá náà, ó rí ère ńlá kan. Ó sọ pé òun máa pa gbogbo àwọn amòye òun títí kan Dáníẹ́lì tí wọn ò bá lè sọ àlá náà, kí wọ́n sì túmọ̀ ẹ̀. (Dán. 2:​3-5) Dáníẹ́lì gbọ́dọ̀ gbé ìgbésẹ̀ kíákíá, àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, ọ̀pọ̀ èèyàn ló máa kú. Torí náà ó “wọlé, ó sì ní kí ọba yọ̀ǹda àkókò fún òun kóun lè sọ ìtumọ̀ àlá náà fún ọba.” (Dán. 2:16) Ẹ ò rí i pé ohun tó ṣe yìí gba ìgboyà àti ìgbàgbọ́! Kò sí àkọsílẹ̀ kankan nínú Bíbélì tó fi hàn pé Dáníẹ́lì ti túmọ̀ àlá rí. Torí náà, ó sọ fún àwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ pé “kí wọ́n gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run fún àánú nípa àṣírí yìí.” (Dán. 2:18) Jèhófà sì dáhùn àdúrà wọn. Ó ran Dáníẹ́lì lọ́wọ́ láti túmọ̀ àlá Nebukadinésárì, ìyẹn ni ò sì jẹ́ kí Dáníẹ́lì àtàwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ kú. w23.08 3 ¶4

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́