-
Ọba Kan Jẹ Èrè Ìgbàgbọ́ Rẹ̀Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
4, 5. (a) Báwo ni Hesekáyà ṣe fi hàn pé òun ò gbára lé Ásíríà? (b) Ìgbésẹ̀ wo ni Senakéríbù gbé láti gbógun ja Júdà, àwọn ìgbésẹ̀ wo sì ni Hesekáyà gbé kí Jerúsálẹ́mù lè bọ́ lọ́wọ́ ìkọlù ojú-ẹsẹ̀? (d) Báwo ni Hesekáyà ṣe wá gbára dì láti gba Jerúsálẹ́mù sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Ásíríà?
4 Àdánwò lílekoko ń bẹ níwájú fún Jerúsálẹ́mù. Hesekáyà ti fòpin sí gbogbo májẹ̀mú tí Áhásì bàbá rẹ̀ aláìnígbàgbọ́ bá àwọn ará Ásíríà dá. Ó tiẹ̀ tún ti tẹ àwọn Filísínì tó jẹ́ alájọṣepọ̀ Ásíríà lórí ba. (2 Àwọn Ọba 18:7, 8) Èyí ti wá bí ọba Ásíríà nínú. Nípa bẹ́ẹ̀, a kà á pé:“Ó ṣẹlẹ̀ ní ọdún kẹrìnlá Hesekáyà Ọba pé Senakéríbù ọba Ásíríà gòkè wá gbéjà ko gbogbo ìlú ńlá olódi ti Júdà, ó sì tẹ̀ síwájú láti gbà wọ́n.” (Aísáyà 36:1) Bóyá Hesekáyà ń fẹ́ dáàbò bo Jerúsálẹ́mù lọ́wọ́ àtakò òjijì látọ̀dọ̀ èṣùbèlèké agbo ọmọ ogun Ásíríà ló ṣe gbà láti san adúrú owó òde tó jẹ́ ọ̀ọ́dúnrún tálẹ́ńtì fàdákà àti ọgbọ̀n tálẹ́ńtì wúrà fún Senakéríbù.a—2 Àwọn Ọba 18:14.
5 Nígbà tí wúrà àti fàdákà tí Hesekáyà rí látinú ìṣúra ọba kò sì tó láti fi san owó tí wọ́n bù lé e, ló bá ko gbogbo àwọn èyí tó jẹ́ ti ohun iyebíye tó lè rí kó nínú tẹ́ńpìlì. Ó tún gé àwọn ilẹ̀kùn tẹ́ńpìlì tí wọ́n fi wúrà bò, ó sì kó wọn ránṣẹ́ sí Senakéríbù. Ìyẹn mú kí ọkàn ará Ásíríà yìí rọ̀, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀ ni. (2 Àwọn Ọba 18:15, 16) Ó jọ pé Hesekáyà mọ̀ pé ará Ásíríà yìí kò ní fi Jerúsálẹ́mù lọ́rùn sílẹ̀ pẹ́ lọ títí. Nítorí náà, wọ́n ní láti gbára dì. Ni àwọn èèyàn bá dínà omi tí àwọn ará Ásíríà tó ń ṣígun bọ̀ lé rí lò. Hesekáyà sì tún mú kí àwọn odi agbára Jerúsálẹ́mù túbọ̀ lágbára sí i, ó sì kó àwọn ohun ìjà jọ pelemọ, títí kan “àwọn ohun ọṣẹ́ lọ́pọ̀ yanturu àti àwọn apata.”—2 Kíróníkà 32:4, 5.
-
-
Ọba Kan Jẹ Èrè Ìgbàgbọ́ Rẹ̀Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
a Iye rẹ̀ ju mílíọ̀nù mẹ́sàn-án ààbọ̀ owó dọ́là (ti ilẹ̀ Amẹ́ríkà) lọ bí a bá gbé e karí ìdiwọ̀n ti lọ́ọ́lọ́ọ́.
-