-
Ońṣẹ́ kan Láti Ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún un LókunKíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
-
-
10 Ìran tí Dáníẹ́lì rí mà kàmàmà o! Ó dájú pé ènìyàn kan lásán kọ́ ni ó rí bí ó ṣe gbójú sókè. Dáníẹ́lì ṣàpèjúwe rẹ̀ kedere pé: “Ara rẹ̀ sì dà bí kírísóláítì, ojú rẹ̀ dà bí ìrísí mànàmáná, ẹyinjú rẹ̀ dà bí ògùṣọ̀ oníná, apá rẹ̀ àti ibi ẹsẹ̀ rẹ̀ dà bí ojú bàbà tí a ha dán, ìró ọ̀rọ̀ rẹ̀ dà bí ìró ogunlọ́gọ̀.”—Dáníẹ́lì 10:6.
-
-
Ońṣẹ́ kan Láti Ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún un LókunKíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
-
-
13 Ìrísí ońṣẹ́ náà tún ba Dáníẹ́lì lẹ́rù, ìyẹn ni bí ara rẹ̀ tí ó rí bí òkúta iyebíye ṣe ń tàn yinrin yinrin, ìrànyòò ojú rẹ̀ dídán tí ó lè múni lójú, bí ìbẹ́ṣẹ̀ṣẹ̀ ẹyinjú rẹ̀ tí ó rí bí iná ṣe ń wọni lára, àti bí apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ alágbára ṣe ń dán gbinrin. Kódà ìró ohùn rẹ̀ alágbára ń kó jìnnìjìnnì báni. Gbogbo èyí fi hàn dájúdájú pé kì í ṣe ènìyàn ẹlẹ́ran ara lásán. Áńgẹ́lì onípò gíga kan, tí ó ń sìn ní ibi mímọ́ níwájú Jèhófà, ni ẹni tí “ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀” yìí ní láti jẹ́, kò lè jẹ́ ẹlòmíràn, ibẹ̀ ni ó sì ti mú ìsọfúnni kan wá.a
-
-
Ońṣẹ́ kan Láti Ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún un LókunKíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
-
-
a Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò dárúkọ áńgẹ́lì yìí, ó dà bí pé òun kan náà ni ẹni tí a gbọ́ ohùn rẹ̀ tí ó ń sọ fún Gébúrẹ́lì pé kí ó ran Dáníẹ́lì lọ́wọ́ nípa ìran tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ rí nígbà yẹn. (Fi Dáníẹ́lì 8:2, 15, 16 wé Da 12:7, 8.) Síwájú sí i, Dáníẹ́lì 10:13 fi hàn pé Máíkẹ́lì, “ọ̀kan nínú àwọn ọmọ aládé tí ó wà ní ipò iwájú pátápátá,” wá ran áńgẹ́lì yìí lọ́wọ́. Nípa báyìí, áńgẹ́lì tí a kò dárúkọ rẹ̀ yìí ti ní àǹfààní láti bá Gébúrẹ́lì àti Máíkẹ́lì ṣiṣẹ́ pọ̀ tímọ́tímọ́.
-