ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w95 7/15 ojú ìwé 32
  • Kí Ni Àwòjíìji náà Ṣí Payá?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí Ni Àwòjíìji náà Ṣí Payá?
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
w95 7/15 ojú ìwé 32

Kí Ni Àwòjíìji náà Ṣí Payá?

WO ÀWÒJÍÌJI kan. Kí ni o rí? Nígbà mìíràn, wíwo àwòjíìji kan fìrí lè ṣí àlèébù kan tí ń tinilójú payá nínú ìrísí rẹ tí inú rẹ yóò dùn láti túnṣe kí àwọn ẹlòmíràn tó kíyèsí i.

Bibeli dàbí àwòjíìji kan gan-an. Ó lè ràn wá lọ́wọ́ láti ní ojú-ìwòye aláìlábòsí nípa ara wa, èyí tí yóò dènà kí a máa ronú púpọ̀ jù—tàbí lọ́nà tí ó kéré jù—nípa bí a ti níyelórí tó lójú Ọlọrun. (Matteu 10:29-31; Romu 12:3) Ní àfikún síi, Bibeli lè ṣí àwọn àlèébù tí ń bẹ nínú àwọn ọ̀rọ̀, ìṣe, tàbí ìṣarasíhùwà wa tí ó yẹ kí a túnṣe payá. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ìwọ yóò ha ṣá ohun tí àwòjíìji náà bá ṣípayá tì bí?

Òǹkọ̀wé Bibeli náà Jakọbu sọ pé: “Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ́ olùgbọ́ ọ̀rọ̀ naa, tí kò sì jẹ́ olùṣe, ẹni yii dàbí ènìyàn kan tí ń wo ojú àdánidá rẹ̀ ninu jígí. Nitori ó wo ara rẹ̀, ó sì lọ kúrò ati lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ó gbàgbé irú ènìyàn tí oun jẹ́.”—Jakọbu 1:23, 24.

Ní òdìkejì ẹ̀wẹ̀, Jakọbu ṣàpèjúwe ọkùnrin mìíràn, bí ẹnì kan tí “ń wo inú òfin pípé naa tí í ṣe ti òmìnira ní àwòfín tí ó sì tẹpẹlẹ mọ́ ọn.” (Jakọbu 1:25) Ọ̀rọ̀ Griki náà tí a túmọ̀ sí ‘wò ní àwòfín’ túmọ̀ sí láti tẹ̀ sẹ́gbẹ̀ẹ́ tàbí garùn wo nǹkan. Ìwé atúmọ́ èdè náà Theological Dictionary of the New Testament sọ pé: “Ọ̀ràn náà ní nínú ju ìwòfìrí lọ́gán lọ.” Ọ̀rọ̀ náà dọ́gbọ́n túmọ̀ sí fífarabalẹ̀ wá ohun kan tí ó farasin. Alálàyé kan lórí Bibeli R. V. G. Tasker kọ̀wé pé: “Ohun kan wà tí ó ṣe pàtàkì tí ẹni tí ń wo nǹkan ní ọkàn-ìfẹ́ láti rí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó lè ṣòro fún un láti rí i kí ó sì lóye ìtúmọ̀ rẹ̀ ní kíámọ́sá.”

Ìwọ yóò ha tipa báyìí yẹ ara rẹ wò fínnífínní nínú àwòjíìji Ọ̀rọ̀ Ọlọrun kí o sì mú ara rẹ bá àwọn ohun tí ó béèrè fún mu bí? Jakọbu ń bá a nìṣó ní sísọ pé: “Ẹni yii, nitori tí oun kò di olùgbọ́ tí ń gbàgbé, bíkòṣe olùṣe iṣẹ́ naa, yoo láyọ̀ ninu ṣíṣe é.”—Jakọbu 1:25.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́