ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àwọn Ìfilọ̀
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—1999 | December
    • Àwọn Ìfilọ̀

      ◼ Ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ tí a ó fi lọni ní oṣù December: Ìmọ̀ Tí Ń Sinni Lọ sí Ìyè Àìnípẹ̀kun pẹ̀lú Ìwé Mímọ́ ní Ìtumọ̀ Ayé Tuntun. January: Ìwé olójú ewé 192 èyíkéyìí tí ìjọ bá ní, tí a ti tẹ̀ jáde ṣáájú ọdún 1986 fún ọrẹ ₦40. Àwọn ìjọ tí kò bá ní irú àwọn ìwé bẹ́ẹ̀ lè fi ìwé Iwọ Le Walaaye Titilae ninu Paradise lori Ilẹ Aye lọni. February: Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé. March: Ìmọ̀ Tí Ń Sinni Lọ sí Ìyè Àìnípẹ̀kun. A óò sapá lákànṣe láti bẹ̀rẹ̀ àwọn ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì inú ilé.

      ◼ Bí ìjọ yín yóò bá yí àwọn àkókò tí ẹ ń ṣe ìpàdé padà lọ́dún tuntun, a rọ gbogbo yín láti máa lọ sí ìpàdé déédéé ní àwọn àkókò tuntun náà. Ẹ sọ fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì àti àwọn olùfìfẹ́hàn yòókù nípa ìyípadà èyíkéyìí tó bá ṣẹlẹ̀, ẹ sì bẹ̀rẹ̀ sí lo àwọn ìwé ìléwọ́ tó ń fi ìṣètò tuntun náà hàn.

      ◼ Kí alábòójútó olùṣalága tàbí ẹnì kan tí ó bá yàn ṣàyẹ̀wò àkáǹtì ìjọ ní December 1 tàbí bí ó bá ti lè yá tó lẹ́yìn náà. Bí ẹ bá ti ṣe èyí, ẹ fi tó ìjọ létí lẹ́yìn tí ẹ bá ti ka ìròyìn ìnáwó tó tẹ̀ lé e.

  • Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Tuntun fún Àpéjọ Àyíká
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—1999 | December
    • Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Tuntun fún Àpéjọ Àyíká

      Àwọn àǹfààní gidi wo lò ń rí gbà nísinsìnyí láti inú rírìn pẹ̀lú Jèhófà? Báwo lo ṣe lè dènà ìdẹwò jíjẹ́ kí àwọn ìlépa tí kì í ṣe ti ìṣàkóso Ọlọ́run ti àwọn ire Ìjọba náà kúrò ní ipò kìíní nínú ìgbésí ayé rẹ? (Mát. 6:33) Ǹjẹ́ ó máa ń ṣòro fún ọ láti mọ ohun tí ó tọ́ yàtọ̀ sí ohun tí kò tọ́ nínú ayé kan tó máa ń mú kí ohun tí kò tọ́ dà bíi pé ó tọ́? (Héb. 5:14) A óò jíròrò àwọn ọ̀ràn wọ̀nyí ní àpéjọ àyíká náà, “Jàǹfààní Nísinsìnyí Nípa Rírìn ní Ọ̀nà Ọlọ́run,” tí yóò bẹ̀rẹ̀ ní oṣù January 2000.—Sm. 128:1.

      Ṣíṣe Ìpàdé Iṣẹ́ Ìsìn tó jẹ́ àwòfiṣàpẹẹrẹ yóò jẹ́ apá tuntun kan ní ọjọ́ Saturday àpéjọ àyíká yìí. Alábòójútó àyíká yín yóò sọ fún àwọn ìjọ nípa àwọn ohun tí a wéwèé, kí gbogbo yín lè múra wá láti gbádùn ìtòlẹ́sẹẹsẹ náà lẹ́kùn-ún rẹ́rẹ́.

      Apá tí a pe àkọlé rẹ̀ ní “Ẹ̀yin Aṣáájú Ọ̀nà—Ẹ Máa Kíyè Sára Gidigidi Nípa Bí Ẹ Ṣe Ń Rìn” yóò fi hàn wá bí a ṣe lè máa lo ọgbọ́n àti òye láti lè máa ra àkókò rírọgbọ padà fún iṣẹ́ òjíṣẹ́ aṣáájú ọ̀nà. (Éfé. 5:15-17) Kókó ọ̀rọ̀ náà, “Ẹ Ṣọ́ra fún Àwọn Ọ̀Ọ̀nà Tó Dà Bí Eyí Tó Tọ́,” yóò kọ́ wa bí a ṣe lè ní ìdánilójú nípa ohun tó ṣètẹ́wọ́gbà fún Ọlọ́run ní gbogbo apá ìgbésí ayé wa. Àsọyé náà, “Bí Àsọtẹ́lẹ̀ Tó Ní Ìmúṣẹ Ṣe Ń Ní Ipa Lórí Wa,” yóò ṣèrànwọ́ láti fi ìfẹ́ fún Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kún èrò inú àti ọkàn-àyà wa. Àsọyé fún gbogbo ènìyàn, tó ní àkọlé náà, “Ọ̀nà Ọlọ́run Ń Ṣàǹfààní Gidigidi!,” yóò tẹnu mọ́ àwọn àǹfààní gidi tí a ń rí gbà nísinsìnyí nínú ṣíṣe gbogbo ohun tí òdodo Jèhófà ń béèrè.

      Ǹjẹ́ o fẹ́ láti fi hàn ní gbangba nípa ìrìbọmi pé o ń fẹ́ láti rìn ní ọ̀nà Ọlọ́run bí ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tó ti ṣèyàsímímọ́? Nígbà náà, bá alábòójútó olùṣalága sọ̀rọ̀, kí ó lè ṣe àwọn ètò tó bá yẹ.

      Jẹ́ kó jẹ́ ìpinnu rẹ láti má ṣe pa àpéjọ àyíká tó bágbà mu yìí jẹ. Wà níbẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ méjèèjì tí ìtòlẹ́sẹẹsẹ náà yóò fi wáyé, nítorí “aláyọ̀ ni gbogbo ẹni tí ó bẹ̀rù Jèhófà, tí ó ń rìn ní àwọn ọ̀nà rẹ̀.”—Sm. 128:1.

  • Ilé Ẹ̀kọ́ Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìṣàkóso Ọlọ́run ti Ọdún 2000
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—1999 | December
    • Ilé Ẹ̀kọ́ Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìṣàkóso Ọlọ́run ti Ọdún 2000

      1 Ilé Ẹ̀kọ́ Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìṣàkóso Ọlọ́run ti jẹ́ ìbùkún ńláǹlà fún àwọn èèyàn Jèhófà. Ní àádọ́ta ọdún tó ti kọjá, ó ti ran àràádọ́ta ọ̀kẹ́ èèyàn lọ́wọ́ láti mú kí wọ́n lè sọ̀rọ̀ dáadáa ní gbangba kí wọ́n sì lè kọ́ni ní òtítọ́ Bíbélì lọ́nà tó gbéṣẹ́. (Sm. 145:10-12; Mát. 28:19, 20) Ǹjẹ́ o ti rí bí ilé ẹ̀kọ́ náà ṣe ràn ọ́ lọ́wọ́? Ó tún lè máa ràn ọ́ lọ́wọ́ nìṣó lọ́dún 2000 bí o bá kópa nínú rẹ̀ lẹ́kùn-ún rẹ́rẹ́, tí o sì ń fi ìmọ̀ràn tí a bá fún ọ sílò.

      2 Ìtọ́ni nípa àwọn iṣẹ́ tí a óò yàn fúnni àti ìtẹ̀jáde tí a óò lò wà lójú ìwé kìíní nínú ìtòlẹ́sẹẹsẹ ilé ẹ̀kọ́ ti ọdún 2000. A sọ àkókò tí a yàn fún apá kọ̀ọ̀kan, ibi tí a ó ti mú ọ̀rọ̀ jáde, bí a ṣe ní láti gbé ọ̀rọ̀ kalẹ̀, àti àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ mìíràn. Jọ̀wọ́, wá àyè, kí o fara balẹ̀ ka ìtọ́ni náà, kí o sì fi wọ́n sílò.

      3 Bíbélì Kíkà Ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀: Apá méjì ni ìtòlẹ́sẹẹsẹ tó wà fún Bíbélì kíkà ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ tí a tó sórí ìtòlẹ́sẹẹsẹ ilé ẹ̀kọ́ pín sí. Ọ̀kan ni ètò gúnmọ́ tó wà fún kíka Bíbélì, tó ń kárí nǹkan bí ojú ìwé márùn-ún nínú Bíbélì. Orí Bíbélì kíkà yìí la máa ń gbé ṣíṣàlàyé àwọn kókó pàtàkì láti inú Bíbélì kà. Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Bíbélì kíkà kejì ni èyí tó jẹ́ àfikún, ó sì máa ń kárí ojú ìwé tó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó ìlọ́po méjì ti àkọ́kọ́. Nípa títẹ̀lé ìtòlẹ́sẹẹsẹ yìí, yóò ṣeé ṣe fún ọ láti ka Bíbélì tán lódindi láàárín ọdún mẹ́ta. A mọ̀ pé àwọn kan lè fẹ́ láti kà ju ohun tí a ṣètò nínú ìtòlẹ́sẹẹsẹ àfikún náà, ó sì lè má ṣeé ṣe fún àwọn míì láti kà tó bẹ́ẹ̀. Dípò tí wàá máa fi ara rẹ wé àwọn ẹlòmíràn, máa yọ̀ nínú ohun tí o bá lè ṣe. (Gál. 6:4) Ohun tó ṣe kókó ni pé kí a máa ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lójoojúmọ́.—Sm. 1:1-3.

      4 Láti forúkọ sílẹ̀ nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìṣàkóso Ọlọ́run, bá alábòójútó ilé ẹ̀kọ́ sọ̀rọ̀. Jọ̀wọ́, máa fi ọwọ́ pàtàkì mú iṣẹ́ tí a bá yàn fún ọ, má sì ṣe kùnà láti ṣe é, àyàfi tó bá di dandangbọ̀n pé kí o yẹ̀ ẹ́ sílẹ̀. Mọrírì ilé ẹ̀kọ́ yìí pé ó jẹ́ ìpèsè látọ̀dọ̀ Jèhófà. Múra sílẹ̀ dáadáa, mọ iṣẹ́ tí a yàn fún ọ dunjú, kí o sì sọ̀rọ̀ tọkàntọkàn, wàá sì tipa báyìí jèrè ní kíkún nínú ilé ẹ̀kọ́ aláìlẹ́gbẹ́ yìí.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́