ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g25 No. 1 ojú ìwé 12-13
  • Máa Ṣoore

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Ṣoore
  • Jí!—2025
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ÌDÍ TÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ FI ṢE PÀTÀKÌ
  • OHUN TÓ O LÈ ṢE
  • A Máa Láyọ̀ Tá A Bá Jẹ́ Ọ̀làwọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2018
  • Jẹ́ Ọ̀làwọ́ Kó O sì Máa Fòye Báni Lò Bíi Ti Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Àwọn Ìlànà Táá Jẹ́ Ká Wà Lálàáfíà Pẹ̀lú Àwọn Èèyàn
    Jí!—2021
  • Èrè Tó Wà Nínú Fífúnni Ní Nǹkan
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2017
Àwọn Míì
Jí!—2025
g25 No. 1 ojú ìwé 12-13
Ìdílé kan jókòó yí tábìlì ká níwájú ilé kékeré tí wọ́n ń gbé, inú wọn ń dùn bí àwọn àti àlejò wọn ṣe ń jẹun.

NǸKAN Ń GBÓWÓ LÓRÍ! ỌGBỌ́N WO LO LÈ DÁ SÍ I?

Máa Ṣoore

Tí owó ọjà tó ń lọ sókè yìí bá ń mú kí àtijẹ àtimu nira fún ẹ, o lè máa wò ó pé ‘ṣé èmi tí mi ò tíì jẹun kánú ni màá wá máa fún àwọn èèyàn ní nǹkan?’ Àmọ́, tó o bá ń ṣoore fáwọn èèyàn, wàá máa láyọ̀ bí nǹkan ò tiẹ̀ rọrùn fún ẹ. Bó o tiẹ̀ ń ṣọ́wó ná, o ṣì lè jẹ́ ọ̀làwọ́.

ÌDÍ TÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ FI ṢE PÀTÀKÌ

Tá a bá ń fún àwọn èèyàn ní nǹkan, tí nǹkan ọ̀hún ò bá tiẹ̀ pọ̀, inú wa máa dùn, àá sì níyì lójú ara wa. Kódà, àwọn onímọ̀ ìṣègùn sọ pé téèyàn bá jẹ́ ọ̀làwọ́, ó máa ń ní ipa tó dáa lórí ìlera ara àti ti ọpọlọ. Bí àpẹẹrẹ, ara onítọ̀hún á máa yá gágá, kò sì ní máa kọ́kàn sókè jù. Ó tún máa ń dín àwọn àìsàn kan kù, bí ẹ̀fọ́rí, ara ríro àti ẹ̀jẹ̀ ríru. Kódà, ó lè jẹ́ kéèyàn rí oorun sùn.

“Ayọ̀ púpọ̀ wà nínú fífúnni ju èyí tó wà nínú rírígbà lọ.”—Ìṣe 20:35.

Tá a bá ń ṣoore fáwọn èèyàn, bóyá a fún wọn lówó tàbí à ń ràn wọ́n lọ́wọ́ láwọn ọ̀nà míì, kò ní ṣòro fún wa láti ní kí wọ́n ran àwa náà lọ́wọ́ tá a bá níṣòro. Ọkùnrin kan tó ń jẹ́ Howard lórílẹ̀-èdè England sọ pé: “Èmi àtìyàwó mi máa ń gbìyànjú láti fún àwọn èèyàn ní nǹkan, a sì máa ń wá bá a ṣe lè ràn wọ́n lọ́wọ́. Torí náà, tá a bá nílò ìrànlọ́wọ́, kì í ṣe wá bíi pé ńṣe là ń da àwọn èèyàn láàmú.” Àmọ́, ó yẹ ká fi sọ́kàn pé tẹ́nì kan bá ń ṣoore fáwọn èèyàn torí pé ó nífẹ̀ẹ́ wọn, kò ní máa retí pé wọ́n gbọ́dọ̀ san oore náà pa dà fóun. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó ṣeé ṣe kóun àtàwọn tó bá ṣoore fún di ọ̀rẹ́, kí wọ́n sì ṣe tán láti ràn án lọ́wọ́ nígbà ìṣòro.

“Ẹ sọ ọ́ di àṣà láti máa fúnni, àwọn èèyàn sì máa fún yín.”—Lúùkù 6:38.

OHUN TÓ O LÈ ṢE

Máa fáwọn èèyàn ní nǹkan. Tó bá tiẹ̀ jẹ́ pé nǹkan díẹ̀ lo ní, o ṣì lè máa fáwọn èèyàn ní nǹkan, bí ò tiẹ̀ ju ìpápánu lọ. Bí àpẹẹrẹ, tálákà ni Duncan àti ìdílé ẹ̀ tí wọ́n ń gbé lórílẹ̀-èdè Uganda, síbẹ̀ wọ́n máa ń fún àwọn èèyàn ní nǹkan. Duncan sọ pé: “Ní gbogbo ọjọ́ Sunday, èmi àtìyàwó mi máa ń rí i pé a pe ẹnì kan wá sílé wa, àá sì jọ wá nǹkan fi panu. A máa ń gbádùn àkókò tá a fi ń wà pẹ̀lú àwọn èèyàn.”

Àmọ́ tó o bá ń ṣoore fáwọn èèyàn, á dáa kó o máa fọgbọ́n ṣe é. Kò ní dáa kí ìdílé ẹ máa jìyà torí pé ò ń ṣoore fáwọn ẹlòmíì.—Jóòbù 17:5.

Gbìyànjú èyí wò: O lè fún ẹnì kan ní ìpápánu tàbí ohun mímu. Tó o bá láwọn nǹkan tó ò lò mọ́, o lè fún àwọn ọ̀rẹ́ tàbí àwọn aládùúgbò tó o mọ̀ pé wọ́n á nílò ẹ̀, tí wọ́n á sì mọyì ẹ̀.


Máa ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ láwọn ọ̀nà míì. Àwọn nǹkan kan wà tó ṣeyebíye tó o lè fún àwọn èèyàn, àmọ́ tí kò ṣeé fowó rà. Bí àpẹẹrẹ, o lè lo àkókò ẹ láti tẹ́tí sí wọn tàbí kó o ràn wọ́n lọ́wọ́ láwọn ọ̀nà míì. Kódà, tó o bá sọ̀rọ̀ tó tuni lára fẹ́nì kan, ẹ̀bùn lo fún un yẹn! Torí náà, jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé o nífẹ̀ẹ́ wọn, o sì mọyì wọn.

Gbìyànjú èyí wò: O lè bá àwọn èèyàn ṣiṣẹ́ nínú ilé wọn tàbí kó o bá wọn tún àwọn nǹkan tó bà jẹ́ ṣe, o sì lè bá wọn ṣe àwọn iṣẹ́ pẹ́ẹ́pẹ̀ẹ̀pẹ́ míì. O lè ṣe káàdì kékeré kan kó o fi ránṣẹ́ sí ọ̀rẹ́ ẹ tàbí kó o kọ ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ sí i pé o kàn ní kó o kí i ni, kó o sì béèrè àlàáfíà ẹ̀.

Ọ̀pọ̀ àǹfààní lo máa rí tó o bá ń gbìyànjú láti máa ṣoore fáwọn èèyàn.

“Ẹ má gbàgbé láti máa ṣe rere, kí ẹ sì máa pín ohun tí ẹ ní pẹ̀lú àwọn ẹlòmíì.”—Hébérù 13:16.

Tọkọtaya kan ń bá ìyá àgbàlagbà kan tún àyíká ilé ẹ̀ ṣe. Ìyá náà gbé tí ì gbígbóná fún tọkọtaya náà bí wọ́n ṣe ń kó àwọn ewé tí wọ́n gbá jọ.
Trey.

“Ilé kékeré là ń gbé, síbẹ̀ a máa ń gba àwọn ọ̀rẹ́ wa lálejò, àá dáná fún wọn, àá sì jọ jẹun. A tún máa ń wá bá a ṣe lè ran àwọn ọ̀rẹ́ wa lọ́wọ́, nígbà míì a lè fún wọn lówó. Àmọ́ lọ́pọ̀ ìgbà, a máa ń lo àkókò wa láti ràn wọ́n lọ́wọ́. Kò sígbà tá a ṣoore fáwọn èèyàn tá ò kì í rí i pé ayọ̀ púpọ̀ wà nínú fífúnni ju rírígbà lọ.”—Trey, Israel.

    Yorùbá Publications (1987-2026)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́