26 Lẹ́yìn náà, àbúrò rẹ̀ jáde, ó sì di gìgísẹ̀ Ísọ̀+ mú, torí náà, ó pe orúkọ rẹ̀ ní Jékọ́bù.*+ Ẹni ọgọ́ta (60) ọdún ni Ísákì nígbà tí Rèbékà bí àwọn ọmọ náà.
36 Ló bá fèsì pé: “Abájọ tí orúkọ rẹ̀ fi ń jẹ́ Jékọ́bù,* ẹ̀ẹ̀mejì+ ló ti gba ipò mi báyìí! Ó ti kọ́kọ́ gba ogún ìbí mi,+ ó tún gba ìbùkún+ tó jẹ́ tèmi!” Ó wá sọ pé: “Ṣé o ò ṣẹ́ ìbùkún kankan kù fún mi ni?”