-
Ẹ́kísódù 27:1-8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
27 “Kí o fi igi bọn-ọ̀n-ní ṣe pẹpẹ;+ kí gígùn rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́* márùn-ún, kí fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún. Kí ẹ̀gbẹ́ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin pẹpẹ náà dọ́gba, kí gíga rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta.+ 2 Kí o ṣe ìwo+ sí igun rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin; àwọn ìwo náà yóò wà lára pẹpẹ náà, kí o sì fi bàbà bo pẹpẹ náà.+ 3 Kí o ṣe àwọn garawa láti máa fi kó eérú* rẹ̀ dà nù, kí o tún ṣe àwọn ṣọ́bìrì, àwọn abọ́, àwọn àmúga àti àwọn ìkóná, bàbà sì ni kí o fi ṣe gbogbo ohun èlò rẹ̀.+ 4 Kí o fi bàbà ṣe àgbàyan* tó rí bí àwọ̀n fún pẹpẹ náà, kí o sì fi bàbà ṣe òrùka mẹ́rin sí igun rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin. 5 Kí o gbé e sí ọwọ́ ìsàlẹ̀ etí pẹpẹ náà, kí àgbàyan náà sì wọnú pẹpẹ náà níbi àárín. 6 Kí o fi igi bọn-ọ̀n-ní ṣe àwọn ọ̀pá fún pẹpẹ náà, kí o sì fi bàbà bò wọ́n. 7 Kí o ki àwọn ọ̀pá náà bọnú àwọn òrùka náà, kí àwọn ọ̀pá náà lè wà ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì pẹpẹ náà nígbà tí wọ́n bá gbé e.+ 8 Kí o ṣe pẹpẹ náà bí àpótí onípákó tí inú rẹ̀ jìn. Kí o ṣe é bí Ó ṣe fi hàn ọ́ lórí òkè gẹ́lẹ́.+
-
-
Ẹ́kísódù 40:10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
10 Kí o fòróró yan pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, kí o sì ya pẹpẹ náà sí mímọ́, kó lè di pẹpẹ mímọ́ jù lọ.+
-