-
Ẹ́kísódù 28:6-8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
6 “Kí wọ́n lo wúrà, fọ́nrán òwú aláwọ̀ búlúù, òwú aláwọ̀ pọ́pù, òwú aláwọ̀ rírẹ̀dòdò àti aṣọ ọ̀gbọ̀ lílọ́ tó dáa láti fi ṣe éfódì, kí wọ́n sì kóṣẹ́ sí i.+ 7 Kí ó ní apá méjì tí wọ́n máa rán pa pọ̀ ní èjìká aṣọ náà. 8 Ní ti àmùrè* tí wọ́n hun,+ èyí tó wà lára éfódì náà láti dì í mú kó lè dúró dáadáa, ohun kan náà ni kí wọ́n fi ṣe é, kí wọ́n lo wúrà, fọ́nrán òwú aláwọ̀ búlúù, òwú aláwọ̀ pọ́pù, òwú aláwọ̀ rírẹ̀dòdò àti aṣọ ọ̀gbọ̀ lílọ́ tó dáa.
-