21 Nínú àgọ́ ìpàdé, lẹ́yìn òde aṣọ ìdábùú tó wà nítòsí Ẹ̀rí náà,+ kí Áárónì àtàwọn ọmọ rẹ̀ ṣètò bí àwọn fìtílà náà á ṣe máa wà ní títàn láti alẹ́ títí di àárọ̀ níwájú Jèhófà.+ Àṣẹ yìí ni kí gbogbo ìran wọn máa tẹ̀ lé títí lọ, kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa ṣe é.+