-
Ẹ́kísódù 36:8-13Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 Lẹ́yìn náà, gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ tó mọṣẹ́+ mú aṣọ mẹ́wàá tó jẹ́ aṣọ ọ̀gbọ̀* lílọ́ tó dáa, tí wọ́n fi ń pa àgọ́, pẹ̀lú fọ́nrán òwú aláwọ̀ búlúù, òwú aláwọ̀ pọ́pù àti òwú aláwọ̀ rírẹ̀dòdò, wọ́n sì fi ṣe àgọ́ ìjọsìn;+ ó* kó iṣẹ́ sí wọn lára, iṣẹ́ náà jẹ́ àwòrán àwọn kérúbù.+ 9 Gígùn aṣọ àgọ́ kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́* méjìdínlọ́gbọ̀n (28), fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin. Ìwọ̀n gbogbo aṣọ àgọ́ náà dọ́gba. 10 Ó wá so márùn-ún nínú aṣọ àgọ́ náà mọ́ra, ó sì so aṣọ àgọ́ márùn-ún yòókù pọ̀. 11 Lẹ́yìn náà, ó fi fọ́nrán òwú aláwọ̀ búlúù ṣe àwọn ihò sí etí aṣọ àgọ́ kọ̀ọ̀kan níbi tó ti so mọ́ ìkejì. Ó ṣe ohun kan náà sí etí aṣọ àgọ́ tó wà ní ìkángun níbi tó yẹ kó ti so pọ̀ mọ́ ti àkọ́kọ́. 12 Ó lu àádọ́ta (50) ihò sí aṣọ àgọ́ kan, ó sì lu àádọ́ta (50) ihò sí aṣọ àgọ́ náà ní ẹ̀gbẹ́ kejì níbi tí yóò ti so pọ̀ kí àwọn ihò náà lè wà ní òdìkejì ara wọn. 13 Níkẹyìn, ó fi wúrà ṣe àádọ́ta (50) ìkọ́, ó sì fi àwọn ìkọ́ náà so àwọn aṣọ àgọ́ náà pọ̀, kí àgọ́ ìjọsìn náà lè di odindi.
-