-
Ẹ́kísódù 29:10-14Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
10 “Kí o mú akọ màlúù náà wá síwájú àgọ́ ìpàdé, kí Áárónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì gbé ọwọ́ wọn lé orí akọ màlúù náà.+ 11 Kí o pa akọ màlúù náà níwájú Jèhófà, lẹ́nu ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.+ 12 Fi ìka rẹ mú lára ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù náà, kí o fi sórí àwọn ìwo pẹpẹ,+ kí o sì da gbogbo ẹ̀jẹ̀ tó kù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.+ 13 Kí o wá mú gbogbo ọ̀rá+ tó bo ìfun, àmọ́ tó wà lára ẹ̀dọ̀ àti kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tó wà lára wọn, kí o fi iná sun wọ́n kí wọ́n lè rú èéfín lórí pẹpẹ.+ 14 Àmọ́ kí o fi iná sun ẹran akọ màlúù náà pẹ̀lú awọ rẹ̀ àti ìgbẹ́ rẹ̀ lẹ́yìn òde àgọ́. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
-