ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 29:10-14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 “Kí o mú akọ màlúù náà wá síwájú àgọ́ ìpàdé, kí Áárónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì gbé ọwọ́ wọn lé orí akọ màlúù náà.+ 11 Kí o pa akọ màlúù náà níwájú Jèhófà, lẹ́nu ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.+ 12 Fi ìka rẹ mú lára ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù náà, kí o fi sórí àwọn ìwo pẹpẹ,+ kí o sì da gbogbo ẹ̀jẹ̀ tó kù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.+ 13 Kí o wá mú gbogbo ọ̀rá+ tó bo ìfun, àmọ́ tó wà lára ẹ̀dọ̀ àti kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tó wà lára wọn, kí o fi iná sun wọ́n kí wọ́n lè rú èéfín lórí pẹpẹ.+ 14 Àmọ́ kí o fi iná sun ẹran akọ màlúù náà pẹ̀lú awọ rẹ̀ àti ìgbẹ́ rẹ̀ lẹ́yìn òde àgọ́. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.

  • Léfítíkù 4:3, 4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 “‘Tí àlùfáà tí ẹ fòróró yàn+ bá dẹ́ṣẹ̀,+ tó sì mú kí àwọn èèyàn jẹ̀bi, kó mú akọ ọmọ màlúù kan tí ara rẹ̀ dá ṣáṣá wá fún Jèhófà, kó fi rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ẹ̀ṣẹ̀ tó dá.+ 4 Kó mú akọ màlúù náà wá sí ẹnu ọ̀nà àgọ́ ìpàdé+ níwájú Jèhófà, kó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé orí akọ màlúù náà, kó sì pa á níwájú Jèhófà.+

  • Léfítíkù 16:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 “Kí Áárónì mú akọ màlúù ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ wá, èyí tó jẹ́ tirẹ̀, kó sì ṣe ètùtù torí ara rẹ̀+ àti ilé rẹ̀.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́