Jẹ́nẹ́sísì 35:22 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 22 Nígbà kan tí Ísírẹ́lì ń gbé ilẹ̀ yẹn, Rúbẹ́nì lọ bá Bílíhà tó jẹ́ wáhàrì* bàbá rẹ̀ sùn, Ísírẹ́lì sì gbọ́ nípa rẹ̀.+ Àwọn ọmọkùnrin Jékọ́bù jẹ́ méjìlá (12). Jẹ́nẹ́sísì 49:4 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 4 Torí ara rẹ kò balẹ̀ bí omi tó ń ru gùdù, o ò ní ta yọ, torí pé o gun ibùsùn+ bàbá rẹ. O sọ ibùsùn mi di ẹlẹ́gbin* nígbà yẹn. Ó gun orí rẹ̀! Léfítíkù 20:11 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 11 Ọkùnrin tó bá bá ìyàwó bàbá rẹ̀ sùn ti dójú ti* bàbá rẹ̀.+ Ẹ gbọ́dọ̀ pa àwọn méjèèjì. Ẹ̀jẹ̀ wọn wà lórí wọn. Diutarónómì 27:20 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 20 “‘Ègún ni fún ẹni tó bá bá ìyàwó bàbá rẹ̀ sùn, torí ó ti dójú ti bàbá rẹ̀.’*+ (Kí gbogbo èèyàn sì sọ pé, ‘Àmín!’) 2 Sámúẹ́lì 16:21 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 21 Áhítófẹ́lì wá sọ fún Ábúsálómù pé: “Bá àwọn wáhàrì* bàbá rẹ lò pọ̀,+ àwọn tó fi sílẹ̀ pé kí wọ́n máa tọ́jú ilé.*+ Gbogbo Ísírẹ́lì á wá gbọ́ pé o ti sọ ara rẹ di ẹni ìkórìíra lójú bàbá rẹ, ọkàn gbogbo àwọn tó ń tì ọ́ lẹ́yìn á sì balẹ̀.” 1 Kọ́ríńtì 5:1 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 5 Ní tòótọ́, wọ́n ròyìn ìṣekúṣe*+ tó ṣẹlẹ̀ láàárín yín, irú ìṣekúṣe* bẹ́ẹ̀ kò tiẹ̀ sí láàárín àwọn orílẹ̀-èdè, pé ọkùnrin kan ń fẹ́* ìyàwó bàbá rẹ̀.+
22 Nígbà kan tí Ísírẹ́lì ń gbé ilẹ̀ yẹn, Rúbẹ́nì lọ bá Bílíhà tó jẹ́ wáhàrì* bàbá rẹ̀ sùn, Ísírẹ́lì sì gbọ́ nípa rẹ̀.+ Àwọn ọmọkùnrin Jékọ́bù jẹ́ méjìlá (12).
4 Torí ara rẹ kò balẹ̀ bí omi tó ń ru gùdù, o ò ní ta yọ, torí pé o gun ibùsùn+ bàbá rẹ. O sọ ibùsùn mi di ẹlẹ́gbin* nígbà yẹn. Ó gun orí rẹ̀!
11 Ọkùnrin tó bá bá ìyàwó bàbá rẹ̀ sùn ti dójú ti* bàbá rẹ̀.+ Ẹ gbọ́dọ̀ pa àwọn méjèèjì. Ẹ̀jẹ̀ wọn wà lórí wọn.
20 “‘Ègún ni fún ẹni tó bá bá ìyàwó bàbá rẹ̀ sùn, torí ó ti dójú ti bàbá rẹ̀.’*+ (Kí gbogbo èèyàn sì sọ pé, ‘Àmín!’)
21 Áhítófẹ́lì wá sọ fún Ábúsálómù pé: “Bá àwọn wáhàrì* bàbá rẹ lò pọ̀,+ àwọn tó fi sílẹ̀ pé kí wọ́n máa tọ́jú ilé.*+ Gbogbo Ísírẹ́lì á wá gbọ́ pé o ti sọ ara rẹ di ẹni ìkórìíra lójú bàbá rẹ, ọkàn gbogbo àwọn tó ń tì ọ́ lẹ́yìn á sì balẹ̀.”
5 Ní tòótọ́, wọ́n ròyìn ìṣekúṣe*+ tó ṣẹlẹ̀ láàárín yín, irú ìṣekúṣe* bẹ́ẹ̀ kò tiẹ̀ sí láàárín àwọn orílẹ̀-èdè, pé ọkùnrin kan ń fẹ́* ìyàwó bàbá rẹ̀.+