ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Léfítíkù 21:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 Jèhófà wá sọ fún Mósè pé: “Sọ fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Áárónì pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú yín ò gbọ́dọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ torí ẹni* tó kú láàárín àwọn èèyàn rẹ̀.+

  • Léfítíkù 21:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Kó má ṣe sún mọ́ òkú ẹnikẹ́ni;*+ tó bá tiẹ̀ jẹ́ bàbá rẹ̀ tàbí ìyá rẹ̀, kò gbọ́dọ̀ fi wọ́n sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.

  • Nọ́ńbà 5:2
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé kí wọ́n ní kí gbogbo adẹ́tẹ̀+ jáde kúrò nínú ibùdó àti gbogbo ẹni tí nǹkan ń dà lára rẹ̀+ pẹ̀lú gbogbo ẹni tí òkú èèyàn*+ ti sọ di aláìmọ́.

  • Nọ́ńbà 6:9
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Àmọ́ tí ẹnì kan bá dédé kú lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀,+ tó sì sọ irun rẹ̀ di aláìmọ́, irun tó fi hàn pé ó ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run,* ó gbọ́dọ̀ fá orí rẹ̀+ ní ọjọ́ tí wọ́n bá kéde pé ó ti di mímọ́. Kó fá a ní ọjọ́ keje.

  • Nọ́ńbà 9:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Ó ṣẹlẹ̀ pé àwọn ọkùnrin kan di aláìmọ́ torí wọ́n fara kan òkú èèyàn,*+ wọn ò wá lè ṣètò ẹbọ Ìrékọjá ní ọjọ́ yẹn. Torí náà, àwọn ọkùnrin náà wá sọ́dọ̀ Mósè àti Áárónì ní ọjọ́ yẹn,+

  • Nọ́ńbà 31:19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 Kí ẹ pàgọ́ sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje. Kí gbogbo ẹ̀yin tí ẹ ti pa èèyàn* àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ ti fara kan ẹni tí wọ́n pa+ wẹ ara yín+ mọ́ ní ọjọ́ kẹta àti ní ọjọ́ keje, ẹ̀yin àti àwọn tí ẹ kó lẹ́rú.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́