8 Màá lọ gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Íjíbítì,+ màá sì mú wọn kúrò ní ilẹ̀ yẹn lọ sí ilẹ̀ kan tó dára, tó sì fẹ̀, ilẹ̀ tí wàrà àti oyin ti ń ṣàn,+ ní agbègbè àwọn ọmọ Kénáánì, àwọn ọmọ Hétì, àwọn Ámórì, àwọn Pérísì, àwọn Hífì àti àwọn ará Jébúsì.+
7 Ẹ ṣẹ́rí pa dà, kí ẹ sì máa lọ sí agbègbè olókè àwọn Ámórì,+ kí ẹ forí lé ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí wọn ká ní Árábà,+ agbègbè olókè, Ṣẹ́fẹ́là, Négébù àti etí òkun, + ilẹ̀ àwọn ọmọ Kénáánì àti Lẹ́bánónì,*+ títí dé odò ńlá, ìyẹn odò Yúfírétì.+
11 Ilẹ̀ tó ní àwọn òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀ ni ilẹ̀ tí ẹ fẹ́ sọdá lọ gbà.+ Òjò tó ń rọ̀ láti ọ̀run ló ń bomi rin ín;+12 Jèhófà Ọlọ́run yín ló ń bójú tó ilẹ̀ náà. Ojú Jèhófà Ọlọ́run yín kì í sì í kúrò ní ilẹ̀ náà, láti ìbẹ̀rẹ̀ ọdún títí di ìparí ọdún.