5 O ò gbọ́dọ̀ forí balẹ̀ fún wọn tàbí kí o jẹ́ kí wọ́n tàn ọ́ láti sìn wọ́n,+ torí èmi Jèhófà Ọlọ́run rẹ jẹ́ Ọlọ́run tó fẹ́ kí o máa sin òun nìkan ṣoṣo,+ tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn bàbá jẹ àwọn ọmọ, dórí ìran kẹta àti ìran kẹrin àwọn tó kórìíra mi,
11 “Fíníhásì+ ọmọ Élíásárì ọmọ àlùfáà Áárónì ti jẹ́ kí inú tó ń bí mi sí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì rọlẹ̀ torí pé kò fàyè gba bíbá mi díje rárá láàárín wọn.+ Ìdí nìyẹn ti mi ò fi pa àwọn ọmọ Ísírẹ́lì run bó tiẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún wọn pé èmi nìkan ṣoṣo ni wọ́n gbọ́dọ̀ máa sìn.+
27 Ọkùnrin náà dáhùn pé: “‘Kí o fi gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo ara* rẹ àti gbogbo okun rẹ àti gbogbo èrò rẹ nífẹ̀ẹ́ Jèhófà* Ọlọ́run rẹ,’+ kí o sì ‘nífẹ̀ẹ́ ọmọnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”+