- 
	                        
            
            Nọ́ńbà 14:28Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        28 Sọ fún wọn pé, ‘“Ó dájú pé bí mo ti wà láàyè,” ni Jèhófà wí, “ohun tí mo gbọ́ tí ẹ sọ+ gẹ́lẹ́ ni màá ṣe sí yín! 
 
- 
                                        
- 
	                        
            
            Nọ́ńbà 14:35Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        35 “‘“Èmi Jèhófà ti sọ̀rọ̀. Ohun tí màá ṣe fún àwọn èèyàn burúkú yìí tí wọ́n kóra jọ láti ta kò mí nìyí: Inú aginjù yìí ni wọ́n máa ṣègbé sí, ibí ni wọ́n sì máa kú sí.+ 
 
- 
                                        
- 
	                        
            
            Nọ́ńbà 32:10-12Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        10 Inú bí Jèhófà gidigidi ní ọjọ́ yẹn débi tó fi búra+ pé: 11 ‘Àwọn ọkùnrin tó kúrò ní Íjíbítì, láti ẹni ogún (20) ọdún sókè kò ní rí ilẹ̀ + tí mo búra pé màá fún Ábúráhámù, Ísákì àti Jékọ́bù,+ torí pé wọn ò fi gbogbo ọkàn wọn tọ̀ mí lẹ́yìn, 12 àfi Kélẹ́bù+ ọmọ Jéfúnè ọmọ Kénásì àti Jóṣúà+ ọmọ Núnì, torí pé wọ́n fi gbogbo ọkàn wọn tọ Jèhófà lẹ́yìn.’+ 
 
- 
                                        
- 
	                        
            
            Diutarónómì 2:14Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        14 Ọdún méjìdínlógójì (38) la fi rìn láti Kadeṣi-bánéà títí a fi sọdá Àfonífojì Séréédì, títí gbogbo ìran àwọn ọkùnrin ogun fi pa run láàárín àpéjọ, bí Jèhófà ṣe búra fún wọn gẹ́lẹ́.+ 
 
- 
                                        
- 
	                        
            
            Sáàmù 95:11Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        11 Torí náà, mo búra nínú ìbínú mi pé: “Wọn ò ní wọnú ìsinmi mi.”+ 
 
-