-
1 Sámúẹ́lì 22:1, 2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
22 Nítorí náà, Dáfídì kúrò níbẹ̀,+ ó sì sá lọ sí ihò Ádúlámù.+ Nígbà tí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ àti gbogbo ilé bàbá rẹ̀ gbọ́, wọ́n lọ bá a níbẹ̀. 2 Gbogbo àwọn tó wà nínú wàhálà, àwọn tó jẹ gbèsè àti àwọn tó ní ẹ̀dùn ọkàn* kóra jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì di olórí wọn. Nǹkan bí ọgọ́rùn-ún mẹ́rin (400) ọkùnrin ló wà pẹ̀lú rẹ̀.
-