ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Sámúẹ́lì 24:6, 7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Ó sọ fún àwọn ọkùnrin rẹ̀ pé: “Jèhófà ò ní fẹ́ gbọ́ rárá pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀ sí olúwa mi, ẹni àmì òróró Jèhófà, pé mo gbé ọwọ́ mi sókè sí i, torí ẹni àmì òróró Jèhófà ni.”+ 7 Ọ̀rọ̀ tí Dáfídì sọ yìí ló fi dá àwọn ọkùnrin tó wà pẹ̀lú rẹ̀ dúró,* kò sì gbà wọ́n láyè láti kọ lu Sọ́ọ̀lù. Àmọ́, Sọ́ọ̀lù dìde, ó kúrò nínú ihò náà, ó sì bá tiẹ̀ lọ.

  • 1 Sámúẹ́lì 26:9
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Àmọ́, Dáfídì sọ fún Ábíṣáì pé: “Má ṣe é ní jàǹbá, ṣé ẹnì kan lè gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ẹni àmì òróró Jèhófà,+ kó má sì jẹ̀bi?”+

  • 1 Sámúẹ́lì 26:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Jèhófà ò ní fẹ́ gbọ́ rárá pé mo gbé ọwọ́ mi sókè sí ẹni àmì òróró Jèhófà!+ Ní báyìí, jọ̀wọ́ jẹ́ ká mú ọ̀kọ̀ àti ìgò omi tó wà níbi orí rẹ̀, kí a sì máa bá tiwa lọ.”

  • Sáàmù 3:1, 2
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 Jèhófà, kí nìdí tí àwọn ọ̀tá mi fi pọ̀ tó báyìí?+

      Kí nìdí tí ọ̀pọ̀ èèyàn fi ń dìde sí mi?+

       2 Ọ̀pọ̀ ń sọ nípa mi* pé:

      “Ọlọ́run ò ní gbà á sílẹ̀.”+ (Sélà)*

  • Sáàmù 7:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 Jèhófà Ọlọ́run mi, ìwọ ni mo fi ṣe ibi ààbò mi.+

      Gbà mí lọ́wọ́ gbogbo àwọn tó ń ṣe inúnibíni sí mi, kí o sì dá mi nídè.+

  • Sáàmù 71:10, 11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ tí kò dáa sí mi,

      Àwọn tó sì fẹ́ gba ẹ̀mí* mi gbìmọ̀ pọ̀,+

      11 Wọ́n ń sọ pé: “Ọlọ́run ti pa á tì.

      Ẹ lé e, kí ẹ sì mú un, torí kò sẹ́ni tó máa gbà á sílẹ̀.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́