-
2 Kíróníkà 14:11Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
11 Ásà wá ké pe Jèhófà Ọlọ́run rẹ̀,+ ó ní: “Jèhófà, kò jẹ́ nǹkan kan lójú rẹ bóyá àwọn tí o fẹ́ ràn lọ́wọ́ pọ̀ tàbí wọn ò lágbára. + Ràn wá lọ́wọ́, Jèhófà Ọlọ́run wa, nítorí ìwọ la gbẹ́kẹ̀ lé,*+ a wá ní orúkọ rẹ láti dojú kọ ọ̀pọ̀ èèyàn yìí.+ Jèhófà, ìwọ ni Ọlọ́run wa. Má ṣe jẹ́ kí ẹni kíkú borí rẹ.”+
-
-
2 Kíróníkà 20:5, 6Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
5 Nígbà náà, Jèhóṣáfátì dìde láàárín ìjọ Júdà àti ti Jerúsálẹ́mù nínú ilé Jèhófà níwájú àgbàlá tuntun, 6 ó sì sọ pé:
“Ìwọ Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá wa, ṣebí ìwọ ni Ọlọ́run ní ọ̀run;+ ṣebí ìwọ lò ń ṣàkóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè?+ Ọwọ́ rẹ ni agbára àti okun wà, kò sì sẹ́ni tó lè dojú kọ ọ́.+
-