-
Diutarónómì 28:15Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
15 “Àmọ́ tí o ò bá pa gbogbo àṣẹ àti òfin Jèhófà Ọlọ́run rẹ mọ́, èyí tí mò ń pa láṣẹ fún ọ lónìí, láti fi hàn pé ò ń fetí sí ohùn rẹ̀, gbogbo ègún yìí máa wá sórí rẹ, ó sì máa bá ọ:+
-
-
2 Kíróníkà 6:36-39Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
36 “Tí wọ́n bá ṣẹ̀ ọ́ (nítorí kò sí èèyàn tí kì í dẹ́ṣẹ̀),+ tí inú rẹ ru sí wọn, tí o fi wọ́n sílẹ̀ fún ọ̀tá, tí àwọn tó mú wọn sì kó wọn lẹ́rú lọ sí ilẹ̀ kan, bóyá èyí tó jìnnà tàbí èyí tó wà nítòsí,+ 37 tí wọ́n bá ro inú ara wọn wò ní ilẹ̀ tí wọ́n kó wọn lẹ́rú lọ, tí wọ́n pa dà sọ́dọ̀ rẹ, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ pé kí o ṣojú rere sí àwọn ní ilẹ̀ tí wọ́n ti jẹ́ ẹrú, tí wọ́n sọ pé, ‘A ti ṣẹ̀, a sì ti ṣàṣìṣe; a ti ṣe ohun búburú,’+ 38 tí wọ́n sì fi gbogbo ọkàn+ wọn àti gbogbo ara* wọn pa dà sọ́dọ̀ rẹ ní ilẹ̀ tí wọ́n ti ń ṣe ẹrú,+ ìyẹn ibi tí wọ́n kó wọn lẹ́rú lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà ní ìdojúkọ ilẹ̀ tí o fún àwọn baba ńlá wọn àti ìlú tí o yàn+ àti ilé tí mo kọ́ fún orúkọ rẹ, 39 nígbà náà, láti ibi tí ò ń gbé ní ọ̀run, kí o gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn pé kí o ṣojú rere sí àwọn,+ kí o sì ṣe ìdájọ́ nítorí wọn, kí o dárí ji àwọn èèyàn rẹ tó ṣẹ̀ ọ́.
-