-
1 Àwọn Ọba 7:16Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
16 Ó fi bàbà rọ ọpọ́n méjì sórí àwọn òpó náà. Gíga ọpọ́n kìíní jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún, gíga ọpọ́n kejì sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún.
-
-
1 Àwọn Ọba 7:20Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
20 Àwọn ọpọ́n náà wà lórí òpó méjì náà, àwọ̀n sì wà lára ibi tó rí rogodo lápá ìsàlẹ̀ ọpọ́n náà; igba (200) pómégíránétì sì wà lórí àwọn ìlà tó yí ọpọ́n kọ̀ọ̀kan ká.+
-
-
Jeremáyà 52:21-23Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
21 Ní ti àwọn òpó náà, gíga ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn jẹ́ ìgbọ̀nwọ́* méjìdínlógún (18), okùn ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ méjìlá (12) lè yí i ká;+ ìnípọn rẹ̀ jẹ́ ìbú ìka* mẹ́rin, ihò sì wà nínú rẹ̀. 22 Bàbà ni wọ́n fi ṣe ọpọ́n tó wà lórí rẹ̀; gíga ọpọ́n kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún;+ bàbà ni wọ́n fi ṣe àwọ̀n àti àwọn pómégíránétì tó yí ọpọ́n náà ká. Òpó kejì dà bíi ti àkọ́kọ́ gẹ́lẹ́, bákan náà sì ni àwọn pómégíránétì rẹ̀. 23 Àwọn pómégíránétì mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún (96) ló wà lẹ́gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ rẹ̀; lápapọ̀, gbogbo pómégíránétì tó yí àwọ̀n náà ká jẹ́ ọgọ́rùn-ún (100).+
-