-
1 Àwọn Ọba 8:37-40Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
37 “Bí ìyàn bá mú ní ilẹ̀ náà+ tàbí tí àjàkálẹ̀ àrùn bá jà, tí ooru tó ń jó ewéko gbẹ tàbí èbíbu+ bá wà, tí ọ̀wọ́ eéṣú tàbí ọ̀yánnú eéṣú* bá wà tàbí tí ọ̀tá wọn bá dó tì wọ́n ní ìlú èyíkéyìí ní ilẹ̀ náà* tàbí tí ìyọnu èyíkéyìí tàbí àrùn bá wáyé,+ 38 àdúrà èyíkéyìí tí ì báà jẹ́, ìbéèrè fún ojú rere+ èyíkéyìí tí ẹnikẹ́ni bá béèrè tàbí èyí tí gbogbo àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì bá béèrè (nítorí pé kálukú ló mọ ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀),+ tí wọ́n bá tẹ́ ọwọ́ wọn sí apá ibi tí ilé yìí wà, 39 nígbà náà, kí o gbọ́ láti ọ̀run, ibi tí ò ń gbé,+ kí o dárí jì wọ́n,+ kí o sì gbé ìgbésẹ̀; kí o san èrè fún kálukú gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ̀,+ nítorí pé o mọ ọkàn rẹ̀ (ìwọ nìkan lo mọ ọkàn gbogbo èèyàn lóòótọ́),+ 40 kí wọ́n lè máa bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọ́n á fi gbé lórí ilẹ̀ tí o fún àwọn baba ńlá wa.
-