-
2 Kíróníkà 6:28-31Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
28 “Bí ìyàn bá mú ní ilẹ̀ náà+ tàbí tí àjàkálẹ̀ àrùn+ bá jà, tí ooru tó ń jó ewéko gbẹ tàbí èbíbu+ bá wà, tí ọ̀wọ́ eéṣú tàbí ọ̀yánnú eéṣú*+ bá wà tàbí tí àwọn ọ̀tá wọn bá dó tì wọ́n ní ìlú èyíkéyìí ní ilẹ̀ náà*+ tàbí tí ìyọnu èyíkéyìí tàbí àrùn bá wáyé,+ 29 àdúrà+ èyíkéyìí tí ì báà jẹ́, ìbéèrè fún ojú rere+ èyíkéyìí tí ẹnikẹ́ni bá béèrè tàbí èyí tí gbogbo àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì bá béèrè (nítorí pé kálukú ló mọ ìṣòro rẹ̀ àti ìrora rẹ̀),+ tí wọ́n bá tẹ́ ọwọ́ wọn sí apá ibi tí ilé yìí wà,+ 30 nígbà náà, kí o gbọ́ láti ọ̀run, ibi tí ò ń gbé,+ kí o sì dárí jì wọ́n;+ kí o san èrè fún kálukú gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ̀, nítorí pé o mọ ọkàn rẹ̀ (ìwọ nìkan lo mọ ọkàn èèyàn),+ 31 kí wọ́n lè máa bẹ̀rù rẹ láti máa rìn ní àwọn ọ̀nà rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọ́n á fi gbé lórí ilẹ̀ tí o fún àwọn baba ńlá wa.
-