17 Èmi yóò sọ̀ kalẹ̀+ wá bá ọ sọ̀rọ̀ níbẹ̀,+ mo máa mú lára ẹ̀mí+ tó wà lára rẹ, màá sì fi sára wọn, wọ́n á sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru ẹrù àwọn èèyàn náà, kí o má bàa dá ru ẹrù náà.+
25 Jèhófà bá sọ̀ kalẹ̀ nínú ìkùukùu,*+ ó bá a+ sọ̀rọ̀, ó sì mú díẹ̀ lára ẹ̀mí+ tó wà lára rẹ̀, ó fi sára àwọn àádọ́rin (70) àgbààgbà náà lọ́kọ̀ọ̀kan. Gbàrà tí ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe bíi wòlíì,*+ àmọ́ wọn ò tún ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.