ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Diutarónómì 6:10-12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 “Tí Jèhófà Ọlọ́run rẹ bá mú ọ dé ilẹ̀ tó búra fún àwọn baba ńlá rẹ Ábúráhámù, Ísákì àti Jékọ́bù pé òun máa fún ọ,+ àwọn ìlú tó tóbi tó sì dára, tí kì í ṣe ìwọ lo kọ́ ọ,+ 11 àwọn ilé tí gbogbo onírúurú ohun rere tí ìwọ kò ṣiṣẹ́ fún kún inú wọn, àwọn kòtò omi tí ìwọ kò gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà àti igi ólífì tí ìwọ kò gbìn, tí o jẹ, tí o sì yó,+ 12 rí i pé o ò gbàgbé Jèhófà,+ ẹni tó mú ọ kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì, kúrò ní ilé ẹrú.

  • Jóòbù 31:24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Tí mo bá gbẹ́kẹ̀ lé wúrà,

      Àbí tí mo sọ fún wúrà tó dáa pé, ‘Ìwọ ni ààbò mi!’+

  • Jóòbù 31:28
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 28 Ẹ̀ṣẹ̀ tí àwọn adájọ́ gbọ́dọ̀ torí ẹ̀ jẹni níyà ni,

      Torí màá ti fìyẹn sẹ́ Ọlọ́run tòótọ́ lókè.

  • Òwe 11:4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  4 Ọrọ̀* kò ní ṣeni láǹfààní ní ọjọ́ ìbínú ńlá,+

      Àmọ́ òdodo ló ń gbani lọ́wọ́ ikú.+

  • Òwe 11:28
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 28 Ẹni tó bá gbẹ́kẹ̀ lé ọrọ̀ rẹ̀ máa ṣubú,+

      Àmọ́ olódodo máa rú yọ bí ewé tútù.+

  • Òwe 23:4, 5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  4 Má fi wàhálà pa ara rẹ torí kí o lè kó ọrọ̀ jọ.+

      Fara balẹ̀ kí o sì lo òye.*

       5 Nígbà tí o bá bojú wò ó, kò ní sí níbẹ̀,+

      Torí ó dájú pé ó máa hu ìyẹ́ bí ẹyẹ idì, á sì fò lọ sójú ọ̀run.+

  • Mátíù 6:19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 “Ẹ má to ìṣúra pa mọ́ fún ara yín ní ayé mọ́,+ níbi tí òólá* ti ń jẹ nǹkan run, tí nǹkan ti ń dípẹtà, tí àwọn olè ń fọ́lé, tí wọ́n sì ń jalè.

  • Mátíù 6:24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 “Kò sí ẹni tó lè sin ọ̀gá méjì; àfi kó kórìíra ọ̀kan, kó sì nífẹ̀ẹ́ ìkejì+ tàbí kó fara mọ́ ọ̀kan, kó má sì ka ìkejì sí. Ẹ ò lè sin Ọlọ́run àti Ọrọ̀.+

  • Máàkù 8:36
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 36 Lóòótọ́, àǹfààní wo ni èèyàn máa rí tó bá jèrè gbogbo ayé, tó sì wá pàdánù ẹ̀mí* rẹ̀?+

  • Lúùkù 12:15
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Ó wá sọ fún wọn pé: “Ẹ la ojú yín sílẹ̀, kí ẹ sì máa ṣọ́ra fún onírúurú ojúkòkòrò,*+ torí pé tí ẹnì kan bá tiẹ̀ ní nǹkan rẹpẹtẹ, àwọn ohun tó ní kò lè fún un ní ìwàláàyè.”+

  • 1 Tímótì 6:17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 Sọ* fún àwọn ọlọ́rọ̀ inú ètò àwọn nǹkan yìí* pé kí wọ́n má ṣe gbéra ga,* kí wọ́n má sì gbẹ́kẹ̀ lé ọrọ̀ tí kò dáni lójú,+ àmọ́ lé Ọlọ́run, ẹni tó ń pèsè gbogbo ohun tí à ń gbádùn fún wa lọ́pọ̀ rẹpẹtẹ.+

  • 1 Jòhánù 2:16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 torí gbogbo ohun tó wà nínú ayé—ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara,+ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ojú+ àti fífi ohun ìní ẹni ṣe àṣehàn*—kò wá látọ̀dọ̀ Baba, àmọ́ ó wá látọ̀dọ̀ ayé.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́