ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 7:23, 24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 23 Ṣùgbọ́n, mo pàṣẹ fún wọn pé: “Ẹ gbọ́ràn sí mi lẹ́nu, màá sì di Ọlọ́run yín, ẹ ó sì di èèyàn mi.+ Kí ẹ máa rìn ní ọ̀nà tí mo pa láṣẹ fún yín, kí nǹkan lè máa lọ dáadáa fún yín.”’+ 24 Ṣùgbọ́n wọn kò tẹ́tí sí mi, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sílẹ̀,+ kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n ń rìn nínú ètekéte* wọn, wọ́n ya alágídí, wọ́n sì ń ṣe ohun tí ọkàn búburú wọn sọ,+ ńṣe ni wọ́n ń pa dà sẹ́yìn, wọn ò lọ síwájú,

  • Jeremáyà 11:7, 8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 Nítorí mo kìlọ̀ fún àwọn baba ńlá yín gidigidi ní ọjọ́ tí mò ń mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì títí di òní, léraléra ni mo sì ń kìlọ̀* fún wọn pé: “Ẹ ṣègbọràn sí ohùn mi.”+ 8 Ṣùgbọ́n wọn ò tẹ́tí sí mi, bẹ́ẹ̀ ni wọn ò fetí sílẹ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, kálukú wọn ya alágídí, wọ́n sì ń ṣe ohun tí ọkàn búburú wọn sọ.+ Torí náà, mo mú gbogbo ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí wá sórí wọn, èyí tí mo pa láṣẹ fún wọn, tí wọn ò sì pa mọ́.’”

  • Míkà 6:16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Torí ò ń tẹ̀ lé òfin Ómírì àti gbogbo ohun tí wọ́n ṣe ní ilé Áhábù,+

      O sì ń tẹ̀ lé ìmọ̀ràn wọn.

      Ìdí nìyẹn tí màá fi mú kí o di ohun tó ń bani lẹ́rù,

      Àwọn tó ń gbé ibẹ̀ yóò sì di ohun àrísúfèé;+

      Àwọn èèyàn yóò sì fi ọ́ ṣẹ̀sín.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́