-
Jóṣúà 4:5-7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
5 Jóṣúà sì sọ fún wọn pé: “Ẹ kọjá síwájú Àpótí Jèhófà Ọlọ́run yín, sí àárín Jọ́dánì, kí ẹnì kọ̀ọ̀kan yín sì gbé òkúta kan sí èjìká rẹ̀, kó jẹ́ iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, 6 kí èyí jẹ́ àmì fún yín. Tí àwọn ọmọ* yín bá bi yín lọ́jọ́ iwájú pé, ‘Kí ni ẹ̀ ń fi àwọn òkúta yìí ṣe?’+ 7 kí ẹ sọ fún wọn pé: ‘Torí omi odò Jọ́dánì tó dáwọ́ dúró níwájú àpótí+ májẹ̀mú Jèhófà ni. Nígbà tí wọ́n gbé àpótí náà sọdá odò Jọ́dánì, omi odò Jọ́dánì dáwọ́ dúró. Àwọn òkúta yìí máa jẹ́ ohun ìrántí fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì títí lọ.’”+
-