Diutarónómì 32:35 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 35 Tèmi ni ẹ̀san àti ìyà ẹ̀ṣẹ̀,+Ní àkókò náà tí ẹsẹ̀ wọn máa yọ̀ tẹ̀rẹ́,+Torí ọjọ́ àjálù wọn sún mọ́lé,Ohun tó sì ń dúró dè wọ́n máa tètè dé.’ Òwe 24:29 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 29 Má sọ pé: “Bó ṣe ṣe sí mi ni màá ṣe sí i pa dà;Màá san ohun tó ṣe pa dà fún un.”*+ Mátíù 5:38, 39 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 38 “Ẹ gbọ́ pé a sọ pé: ‘Ojú dípò ojú àti eyín dípò eyín.’+ 39 Àmọ́ mò ń sọ fún yín pé: Ẹ má ṣe ta ko ẹni burúkú, àmọ́ ẹnikẹ́ni tó bá gbá yín ní etí* ọ̀tún, ẹ yí èkejì sí i.+ Róòmù 12:17 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 17 Ẹ má ṣe fi ibi san ibi fún ẹnikẹ́ni.+ Ẹ jẹ́ kí ìrònú yín dá lé ohun tó dára lójú gbogbo èèyàn. Róòmù 12:19 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 19 Ẹ má ṣe fúnra yín gbẹ̀san, ẹ̀yin olùfẹ́, àmọ́ ẹ fàyè sílẹ̀ fún ìrunú;*+ nítorí ó ti wà lákọsílẹ̀ pé: “Tèmi ni ẹ̀san; màá gbẹ̀san, ni Jèhófà* wí.”+ 1 Tẹsalóníkà 5:15 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 15 Ẹ rí i pé ẹnikẹ́ni ò fi búburú san búburú fún ẹnì kankan,+ kí ẹ sì máa fìgbà gbogbo wá ohun rere fún ara yín àti fún gbogbo àwọn míì.+
35 Tèmi ni ẹ̀san àti ìyà ẹ̀ṣẹ̀,+Ní àkókò náà tí ẹsẹ̀ wọn máa yọ̀ tẹ̀rẹ́,+Torí ọjọ́ àjálù wọn sún mọ́lé,Ohun tó sì ń dúró dè wọ́n máa tètè dé.’
38 “Ẹ gbọ́ pé a sọ pé: ‘Ojú dípò ojú àti eyín dípò eyín.’+ 39 Àmọ́ mò ń sọ fún yín pé: Ẹ má ṣe ta ko ẹni burúkú, àmọ́ ẹnikẹ́ni tó bá gbá yín ní etí* ọ̀tún, ẹ yí èkejì sí i.+
19 Ẹ má ṣe fúnra yín gbẹ̀san, ẹ̀yin olùfẹ́, àmọ́ ẹ fàyè sílẹ̀ fún ìrunú;*+ nítorí ó ti wà lákọsílẹ̀ pé: “Tèmi ni ẹ̀san; màá gbẹ̀san, ni Jèhófà* wí.”+
15 Ẹ rí i pé ẹnikẹ́ni ò fi búburú san búburú fún ẹnì kankan,+ kí ẹ sì máa fìgbà gbogbo wá ohun rere fún ara yín àti fún gbogbo àwọn míì.+