ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Sámúẹ́lì 19:4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 4 Torí náà, Jónátánì sọ̀rọ̀ Dáfídì ní rere+ níwájú Sọ́ọ̀lù bàbá rẹ̀. Ó sọ fún un pé: “Kí ọba má ṣàìdáa sí* Dáfídì ìránṣẹ́ rẹ̀, nítorí kò ṣẹ̀ ọ́, àwọn ohun tó ṣe fún ọ sì ti ṣe ọ́ láǹfààní.

  • 1 Sámúẹ́lì 25:23, 24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 23 Nígbà tí Ábígẹ́lì tajú kán rí Dáfídì, ní kíá ó sọ̀ kalẹ̀ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó kúnlẹ̀, ó sì dojú bolẹ̀ níwájú Dáfídì. 24 Ó kúnlẹ̀ síbi ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì sọ pé: “Olúwa mi, jẹ́ kí ẹ̀bi náà wà lórí mi; jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ bá ọ sọ̀rọ̀, kí o sì fetí sí ọ̀rọ̀ tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ fẹ́ sọ.

  • Ẹ́sítà 4:13, 14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 ó fún Ẹ́sítà lésì pé: “Má rò pé ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí gbogbo àwọn Júù yòókù kò ní kàn ọ́ torí pé o wà nínú agbo ilé ọba. 14 Tí o bá dákẹ́ ní àkókò yìí, àwọn Júù máa rí ìtura àti ìdáǹdè láti ibòmíì,+ ṣùgbọ́n ìwọ àti ilé bàbá rẹ yóò ṣègbé. Ta ló sì mọ̀ bóyá torí irú àkókò yìí lo fi dé ipò ayaba tí o wà?”+

  • Sáàmù 145:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Wọ́n á máa kéde ògo ìjọba rẹ,+

      Wọ́n á sì máa sọ̀rọ̀ nípa agbára rẹ,+

  • Òwe 9:8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  8 Má ṣe bá afiniṣẹ̀sín wí, torí á kórìíra rẹ.+

      Bá ọlọ́gbọ́n wí, yóò sì nífẹ̀ẹ́ rẹ.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́