-
1 Àwọn Ọba 18:24, 25Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
24 Lẹ́yìn náà, kí ẹ pe orúkọ ọlọ́run yín,+ èmi náà á pe orúkọ Jèhófà. Ọlọ́run tí ó bá fi iná dáhùn ni Ọlọ́run tòótọ́.”+ Gbogbo àwọn èèyàn náà bá dáhùn pé: “Ohun tí o sọ dáa.”
25 Èlíjà wá sọ fún àwọn wòlíì Báálì pé: “Ẹ mú akọ ọmọ màlúù kan, kí ẹ sì kọ́kọ́ ṣètò rẹ̀, nítorí pé ẹ̀yin ni ó pọ̀ jù. Kí ẹ wá pe orúkọ ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n kí ẹ má fi iná sí i.”
-